“Ọ̀run ńyabọ̀, ki ṣé ọ̀rọ̀ ẹnìkan”: “The sky is falling, is not a matter limited to a person”.

Ọ̀run ńyabọ̀ - the sky is falling

Ọ̀run ńyabọ̀ – the sky is falling. Courtesy: @theyroubablog

Òwe Yorùbá yi ṣe gba àwọn ti o nbẹ̀rù nigba gbogbo níyànjú wípé ó yẹ ki èniyàn fara balẹ̀ lati ṣe iwadi ohun ti ó fẹ́ ṣẹlẹ̀ ki ó tó “kú sílẹ̀ de ikú”.

Ẹlòmíràn, kò ni ṣe iwadi ohun ti àwọn èniyàn fi ńsáré, ki ó tó bẹ̀rẹ̀ si sáré.  Ọpọlọpọ ti sa wọ inú ewu ti wọn rò wípé àwọn sá fún.  Fún àpẹrẹ, nigbati iná ajónirun balẹ̀ ni àgọ́ Ológun ni Ikẹja ni ìlú Èkó ni bi ọdún mẹjọ sẹhin.  Bi àwọn kan ti gbọ́ ìró iná ajónirun yi, wọn sáré titi ọpọ fi parun si inú irà ni Ejigbo ni ọ̀nà jínjìn si ibi ti ìṣẹ̀lẹ̀ ti ṣẹlẹ̀.

Àpẹrẹ miran ti a lè fi ṣe àlàyé pé “Ọ̀run ńyabọ̀, ki ṣé ọ̀rọ̀ ẹnìkan” ni ẹni ti ó sọ pé ohun ri wípé ayé ti fẹ parẹ́, àwọn kan gbàgbọ́, wọn bẹ̀rẹ̀ si ta ohun ìní wọn.  Àti ẹni ti ó ta ohun ìní àti ẹni ti ó ra, kò si ninú wọn ti ó ma mú nkankan lọ ti ayé bá parẹ nitotọ.

ENGLISH TRANSLATION

This Yoruba proverb can be used to encourage those who are always afraid, that it is good to be patient enough to find out the happenings before “dying in readiness for death”.

Some, will not enquire about why people are running before they begin to run too.  Many have ran into danger that they thought they were trying to escape.  An example, was when there was bomb explosion at the Ikeja Cantonment, Lagos about eight years ago.  When some heard the explosion, they ran until they perished at the Ejigbo marsh, a far distance from the incident.

Another example that can be used to buttress the proverb that “The sky is falling, is not a matter limited to a person”, was when a soothsayer predicted that the world was coming to an end at the beginning of the new millennium, many believed and they began to sell off their properties.  Both the property seller and the property buyer, none would take along anything were the world to have come to an end as predicted.

Share Button

Originally posted 2013-09-27 18:37:30. Republished by Blog Post Promoter

“Olúróhunbí jẹ́ ẹ̀jẹ́ ohun ti kò lè san”: “Olurohunbi made a vow/covenant she could not keep”

Yorùbá ka ọmọ bibi si ohun pàtàki fún ìdílé, nitori èyi, tijó tayọ̀ ni Yorùbá ma fi nki ọmọ titun káàbọ̀ si ayé.  Gẹ́gẹ́bí Ọ̀gá ninu Olórin ilẹ̀-aláwọ̀ dúdú, Olóyè Ebenezer Obey ti kọ́ “Ẹ̀bùn pàtàki ni ọmọ bibi…”.  Ìlú ti igbe ọmọ titun kò bá dún, ìlú naa ́a kan gógó.  Eleyi lo ṣẹlẹ̀ ni ìlú Olúróhunbí.

Fún ìgbà pípẹ́, àwọn obinrin ìlú kò ri ọmọ bi, nitorina, gbogbo wọn lọ si ọ̀dọ̀ Òrìṣà Ìrókò lati lọ tọrọ ọmọ.  Oníkálukú wọn jẹjẹ oriṣiriṣi ohun ti wọn ma fún Ìrókò ti wọ́n bá lè ri ọmọ bi.  Ẹlòmiràn jẹ ẹ̀jẹ́ Ewúrẹ́, òmíràn Àgùntàn tàbi ohun ọ̀gbìn.  Yorùbá ni “Ẹyin lohùn, bi ó bá balẹ̀ ko ṣẽ ko”, kàkà ki Olurohunbi, ìyàwó Gbẹ́nàgbẹ́nà, jẹ ẹ̀jẹ́ ohun ọ̀sìn tàbi ohun àtọwọ́dá, o jẹ ẹ̀jẹ́ lọ́dọ̀ Ìrókò pé ti ohun bá lè bi ọmọ, ohun yio fún Ìrókò lọ́mọ naa.

Lai pẹ́, àwọn obinrin ìlú bẹ̀rẹ̀ si bimọ.  Oníkálukú pada si ọ̀dọ̀ Ìrókò lati lọ san ẹ̀jẹ́ wọn, ṣùgbọ́n Olúróhunbí kò jẹ́ mú ọmọ rẹ̀ silẹ lati san ẹ̀jẹ́ ti ó jẹ́. 

Òwe Yorùbá ni  “Bi ojú bá sé  ojú, ki ohun má yẹ̀ ohun”, ṣùgbọ́n

Ọmọ titun – a baby
Ọmọ titun – a baby Courtesy: @theyorubablog

 Olúróhunbí ti gbàgbé ẹ̀jẹ́ ti ó jẹ́. 

Ni ọjọ́ kan, Olúróhunbí dágbére fún ọkọ rẹ̀ pé ohun fẹ́ lọ si oko ẹgàn/igbó, ó bá gba abẹ́ igi Ìrókò kọjá.  Bi ó ti dé abẹ́ igi Ìrókò, Ìrókò gbamú, ó bá sọ di ẹyẹ.  Ẹyẹ Olúróhunbí bẹ̀rẹ̀ si kọ orin lóri igi Ìrókò bayi:

 

Oníkálukú jẹ̀jẹ́ Ewúrẹ́, Ewúrẹ́
Ònìkàlùkú jẹjẹ Àgùntàn, Àgùntàn bọ̀lọ̀jọ̀
Olúróhunbí jẹ̀jẹ́ ọmọ rẹ̀, ọmọ rẹ̀ a pọ́n bí epo,
Olúróhunbí o, jain jain, Ìrókó jaini (2ce)

Nigbati, ọkọ Olúróhunbí reti iyàwó rẹ titi, ó bá pe ẹbi àti ará lati wa.  Wọn wa Olúróhunbí titi, wọn kò ri, ṣùgbọ́n nigbati ọkọ rẹ̀ kọjá lábẹ́ igi Ìrókò to gbọ́ orin ti ẹyẹ yi kọ, ó mọ̀ pe ìyàwó ohun ló ti di ẹyẹ.

Gẹgẹbi iṣẹ́ rẹ (Gbénàgbénà), ó gbẹ́ èrè bi ọmọ, ó múrá fún, ó gbe lọ si abẹ́ igi Ìrókò.  Òrìṣà inú igi Ìrókò, ri ère ọmọ yi, o gbã, ó sọ Olúróhunbí padà si ènìà.

Ìtàn yi kọ́ wa pé: igbèsè ni ẹ̀jẹ́, ti a bá dá ẹ̀jẹ́, ki á gbìyànjú lati san; ki a má da ẹ̀jẹ́ ti a kò lè san àti ki á jẹ́ ki ọ̀rọ̀ wa jẹ ọ̀rọ̀ wa. Continue reading

Share Button

Originally posted 2015-03-27 09:20:46. Republished by Blog Post Promoter

“Ori bí bẹ́, kọ́ ni oògùn ori-fí fọ́” – A fi àsikò ọdún Keresimesi mú òbi àwọn ọmọbinrin ilé-iwé Chibok ti won ji ko, lọ́kàn le – Cutting off the head is not the antidote for headache – Using the Christmas season to encourage parents of the abducted Chibok School Girls to keep hope alive.

Yorùbá ni “Ibi ti ẹlẹ́kún ti nsun ẹkún ni aláyọ̀ gbe nyọ́”.  Òwe yi fihan ohun tó nṣẹlẹ̀ ni àgbáyé.  Bi ọ̀pọ̀ àwọn ti ó wà ni Òkè-òkun ti nra ẹ̀bùn àti ọ̀pọ̀ oúnjẹ ni oriṣiriṣi fún ọdún, bẹni àwọn ti kò ni owó lati ra oúnjẹ pọ ni àgbáyé.  Eyi ti ó burú jù ni àwọn ti ó wà ninú ibẹ̀rù pàtàki àwọn Onígbàgbọ́ ti kò lè lọ si ile-ijọsin lati yọ ayọ̀ ọdún iranti ọjọ́ ibi Jesu nitori ibẹ̀rù àwọn oniṣẹ ibi.

Gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ Yorùbá ti ó ni “Ori bí bẹ́, kọ́ ni oògùn ori-fí fọ́”. Bawo ni pi pa èniyàn nitori kò gba ẹ̀sìn ṣe lè mú ki èrò pọ̀ si ni irú ẹ̀sìn bẹ́ ẹ̀?  Òkè-Ọya ni Àriwá Nàíjírià, Boko Haram npa èniyàn pẹ̀lú ibọn àti ohun ijà ti àwọn ti ó ka iwé ṣe, bẹni wọn korira, obinrin, iwé kikà, ẹlẹ́sìn- ìgbàgbọ́ ni Òkè-Ọya àti ẹni ti ó bá takò wọn pé ohun ti wọn nṣe kò dára.  Pi pa èniyàn kọ ni yio mu ki àwọn ará ilú gba ẹ̀sìn.

Free the Chibok Girls

Nigerian women protest against Government’s failure to rescue the abducted Chibok School Girls

A ki àwọn iyá àti bàbá àwọn ọmọ obirin ilú Chibok ti wọn ji kó lọ́ ni ilé-iwé, àwọn ẹbi ti ó pàdánù ọmọ, iyàwó, ọkọ, ẹbi, ará àti ọ̀rẹ́ lọ́wọ́ àwọn oníṣẹ́ ibi – Boko Haram, pé ki Ọlọrun ki ó tù wọn ninú.  A fi àsikò ọdún Keresimesi mú òbi àwọn ọmọbinrin ilé-iwé Chibok ti won ji ko, lọ́kàn le, pé ki wọn ma ṣe sọ ìrètí nù, nitori “bi ẹ̀mi bá wà ìrètí nbẹ”.

 

ENGLISH TRANSLATION

According to Yoruba saying “As some are mourning, some are rejoicing”.  This adage is apt to describe the happenings around the world.  As many Oversea or in the developed World are spending huge sum for gifts and so much food for the yuletide, so also are many people in the world facing starvation as they have no money to buy food.  The worst, are those living in fear particularly the Christians that cannot go to places of worship to celebrate Christmas because of fear of the terrorists. Continue reading

Share Button

Originally posted 2014-12-23 21:35:53. Republished by Blog Post Promoter

“BÍ ỌMỌDÉ BÁ ṢUBÚ Á WO IWÁJÚ…”: “IF A CHILD FALLS HE/SHE LOOKS FORWARD…”

BÍ ỌMỌDÉ BÁ ṢUBÚ Á WO IWÁJÚ, BÍ ÀGBÀ BÁ ṢUBÚ Á WO Ẹ̀HÌN

Òwe Yorùbá yi wúlò lati juwe òye àgbàlagbà lati wo ẹ̀hìn fún ẹ̀kọ́ nínú ìrírí tó ti kọjá lati yanjú ọ̀ràn tó ṣòro nígbàtí ọmọdé tí kò rí irú ìṣòro bẹ̃ lati kọ́ ọgbọ́n, má nwo iwájú.

Ọ̀rọ̀ Yorùbá miran ni “Ẹni tó jìn sí kòtò, kọ ará yókù lọ́gbọ́n”.  Nitotọ ọ̀rọ̀ miran sọ wípé “Ìṣòro ni Olùkọ́ tó dára jù”, ṣùgbọ́n dí dúró kí ìṣòro jẹ Olukọ fún ni lè fa ewu iyebíye, nitorina ó dára ká kọ́ ọgbọ́n lati ọ̀dọ̀ àgbà.  Ọlọ́gbọ́n ma nlo ọgbọ́n ọlọ́gbọ́n lati yẹra fún ìṣubú.

Ní àsìkò ẹ̀rọ ayélujára yi, òwe “Bí ọmọdé bá ṣubú á wo iwájú, bí àgbà bá ṣubú á wo ẹ̀hìn” ṣi wúlò fún àwọn ọmọdé tí ó lè ṣe àṣàyàn lati fi etí si àgbà, kọ́ ẹ̀kọ́, tàbí ka àkọsílẹ̀ ìrírí àgbà nínú ìwé tàbí lórí ayélujára lati yẹra fún àṣìṣe, kọ́ ibi tí agbára àti àilera àgbà wà fún lílò lọ́jọ́ iwájú.

ENGLISH TRANSLATION

IF A CHILD FALLS HE/SHE LOOKS FORWARD, IF AN ELDER FALLS HE/SHE LOOKS BACK

This Yoruba proverb is relevant to describe the ability of an adult to look back and draw from past experience to solve a problem while a child with no previous experience look forward since he/she has no previous experience to fall back on.

There is another Yoruba proverb that said “The one that fell into a ditch teaches the others wisdom”. Though there is an adage that said “Experience is the best Teacher”, often waiting to learn from personal experience may be too costly, so it is better to avoid the cost by learning a lesson from the Elders.  The wise people would always learn from the experience of others to avoid pitfalls.

In this computer age, the proverb that said “if a child falls he/she looks forward, if an elder falls he/she looks back” is still relevant to encourage the young ones, who have more choices of listening and learning directly from the elder or reading the documented experience of others from books or the internet to avoid past mistakes, learn from the strength and weakness of the Elders for future use.

Share Button

Originally posted 2013-05-03 19:29:24. Republished by Blog Post Promoter

“Ará Ilú Nigeria: “Fi Ẹ̀tẹ̀ silẹ̀ pa Làpálàpá” – Nigerians are: Ignoring Leprosy for the cure of Ringworm”

Ẹ̀tẹ̀ tó mbá ilú jà ni ‘iwà-ibàjẹ́’.  Ìyà ti ará ilú njẹ lọ́wọ́lọ́wọ́, ki i ṣe èrè iwà-ibàjẹ́ ọdún kan, ṣùgbọ́n  ti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún.  Kò si ìfẹ́ ilú, nitori eyi, àwọn oniwà ibàjẹ́ ni àwọn ará ilú nyin bi wọn bá ti ẹ fi èrú kó owó jọ pàtàki ni ilé ìjọ́sìn, wọn kò ri ẹni ba wọn wi.

Ojú Olé Rè é – Looters of Nigeria. Courtesy: @theyorubablog

Ojú Olé Rè é – Looters of Nigeria. Courtesy: @theyorubablog

Fún akiyesi, ilé iṣẹ́ ti ó n pèsè iná mọ̀nàmọ́ná, owó ti Ìjọba àpa-pọ̀ ba pin lati pèsè iná mọ̀nàmọ́ná fún gbogbo ará ilú, ọ̀gá ilé-iṣẹ́ á pin pẹ̀lú àwọn Ìjọba Ológun tàbi Òṣèlú Alágbádá.  Ni bi ọgbọ̀n ọdún sẹhin, nigbati àwọn ọmọ iṣẹ́ ri pé àwọn ọ̀gá ti ó nji owó, kò si ẹni ti ó mú wọn, àwọn na a brẹ̀rẹ̀ si lọ yọ nkan lára ẹ̀rọ ti ó gbé iná wọ àdúgbò lati lè gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ lọ́wọ́ ará àdúgbò.  Ará àdúgbò á dá owó ki àwọn òṣiṣẹ́ ilé-iṣẹ́ mọ̀nàmọ́ná tó wá tú ohun ti ó bàjẹ́ tàbi ohun ti wọn yọ ṣe.

Kàkà ki ará ilú para-pọ̀ lati wo ẹ̀tẹ̀ san, nipa gbi gbé ogun ti iwà-ibàjẹ́ ni ilé-iṣẹ́ mọ̀nàmọ́ná, onikálùkù bẹ̀rẹ̀ si ṣètò fún ará wọn nipa ri ra ẹ̀rọ́ iná mọ̀nàmọ́ná ti àwọn Òyinbó ngbe dani nigbati wọn bá fẹ lọ pàgọ́.  Àwọn ẹ̀rọ wọnyi kò lágbára tó lati dipò iná mọ̀nàmọ́ná ti ó yẹ ki Ìjọba pèsè.  Àwọn ará ilú kò ro ìnáwó ti ó kó wọn si, ariwo, àti èéfín burúkú ti ẹ̀rọ yi nfẹ sinú afẹ́fẹ́.  Àwọn ti ó nja ilú lólè ni ó nkó ẹ̀rọ wọnyi wọlé, wọn kò gbèrò ki iná mọ̀nàmọ́ná wa nitori wọn kò ni ri ẹni ra ọjà wọn.   Wọn rò wi pé àwọn lè dá ilé-iṣẹ́ ti ó n pèsè iná mọ̀nàmọ́ná silẹ̀ ti ó lè lo atẹ́gùn, omi, epo rọ̀bì, oòrùn lati pèsè iná ti kò léwu bi ẹ̀rọ́ iná mọ̀nàmọ́ná.

Ẹ̀tẹ̀ ṣòro lati wòsàn ju làpálàpá lọ, ibàjẹ́ ló yára lati ṣe ju lati tú nkan ṣe lọ. O ye ki ará ilú para pọ̀ pẹ̀lú Ìjọba lọ́wọ́lọ́wọ́, lati gbé ogun ti iwà ibàjẹ́ àti àwọn aṣèbàjẹ́, ju pé ki wọn fi ara gbi gbóná kọ ìyà ọgbọ̀n ọdún laarin ọdún kan tàbi meji.

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button

Originally posted 2016-05-17 21:34:04. Republished by Blog Post Promoter

ÌPANU – SNACKS

Yorùbá ka ìpanu si ohun ti anjẹ lati mu inu duro pataki ni arin ounje aro ati ale.  A le ka si ounje osan.

Traditionally, Yoruba people regard snacks as stop-gap chewable, particularly between breakfast and dinner.  These are also often regarded as lunch. The most popular traditional Yoruba snacks are below: Continue reading

Share Button

Originally posted 2013-02-22 18:41:13. Republished by Blog Post Promoter

Ọdún tuntun káàbọ̀ – Ẹgbà-lé-mẹ́rìnlà – Welcoming the New Year – 2014

Ẹ kú ọdún o – Season Greetings. Courtesy: @theyorubablog

kú dún

Festive Greetings

 kú ìyè dún

Greetings on the return of the year

dún á ya abo

Prosperous New Year  

À èyí ṣe àmọ́dún o.                                                  Better years ahead

View more presentations or Upload your own.
Share Button

Originally posted 2013-12-31 23:11:39. Republished by Blog Post Promoter

“Àjẹ ìwẹ̀hìn ló ba Ẹlẹ́dẹ̀ jẹ́” – Ìkìlọ̀: ẹ jẹun díẹ̀ – Ẹ kú ọdún o, à ṣèyí ṣè àmọ́dún o – “Eating without looking back, is the cause of disgrace for the Pig” – Caution: eat moderately during the Yuletide.

Iyán àti ẹ̀fọ́ rírò – Pounded Yam and mixed stewed vegetable soup. Courtesy: @theyorubablog

Ni asiko ọdún, pataki, asiko ọdún iranti ọjọ ibi Jesu, bi oúnjẹ ti pọ̀ tó fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ti o wa ni Òkè-okun àti àwọn díẹ̀ ni ilẹ̀ aláwọ̀ dúdú, bẹ̃ ni o ṣọ̀wọ́n tó fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àgbáyé.

Ò̀we Yorùbá ni, “Ọ̀kánjúwà-á bu òkèlè, ojú rẹ à lami”.  Bi enia ò bá ni ọ̀kánjúwà, á mọ irú òkèlè ti ó lè gba ọ̀nà ọ̀fun rẹ, ṣùgbọ́n ọ̀kánjúwa á bu  lai ronu pe òkèlè ti ó ju ọ̀nà ọ̀fun lọ á fa ẹkún.  Òwe yi bá àwọn ti ó ṣe jura wọn lọ tàbi ki ó jẹ igbèsè lati ra ẹ̀bùn, oúnjẹ ti wọn ò ni jẹ tán, aṣọ, bàtà àti oriṣiriṣi ti wọn ri ni ìpolówó lai mọ̀ pé ọdún á ré kọjá.  Lẹhin ọdún, ọ̀pọ̀ a fi igbèsè bẹ̀rẹ̀ ọdún titun,  eyi a fa ìrora àti ọ̀rọ̀ ti ó ṣòro si ayé irú ẹni bẹ̃.

Àjẹ ìwẹ̀hìn ló ba Ẹlẹ́dẹ̀ jẹ́ – Eating without looking back, is the cause of disgrace for the Pig. Courtesy: @theyorubablog

Yorùbá ni “Ájẹ ìwẹ̀hìn ló ba Ẹlẹ́dẹ̀ jẹ”, nitori eyi ìkìlọ̀ fún ẹ̀yin ti ẹ ni ìfẹ́ àti gbé èdè àti àṣà̀̀ Yorùbá lárugẹ, pe ki ẹ ṣe ohun gbogbo ni ìwọ̀ntúnwọ̀nsì.

Ẹ kú ọdún o, ọdún titun ti o ḿbọ̀ lọ́nà á ya abo fún gbogbo wa.

ENGLISH TRANSLATION

During this yuletide, particularly during the remembrance of Jesus’ birth – Christmas celebration, as there is abundance of food for many people in the developed world and some in Africa so also is scarcity for many others all over the world.  Continue reading

Share Button

Originally posted 2013-12-24 23:01:10. Republished by Blog Post Promoter

Bi ọmọ ò jọ ṣòkòtò á jọ kíjìpá: Ibáṣe pọ Idilé Yorùbá – If a child does not take after the father, he/she should take after the mother – Yoruba Family Relationship

Bàbá, iyá àti ọmọ ni wọn mọ si Idilé ni Òkè-òkun ṣùgbọ́n ni ilẹ̀ Yorùbá kò ri bẹ́ ẹ̀, nitori ẹbi Eg bàbá, ẹ̀gbọ́n àti àbúrò ẹni, ọmọ, ọkọ àti aya wọn ni a mọ̀ si Idilé.  Yorùbá fẹ́ràn lati má a bọ̀wọ̀ fún àgbà nitori eyi, ẹni ti ó bá ju Bàbá àti Ìyá ẹni lọ Bàbá tàbi Ìyá la n pè é, wọn ki pe àgbà ni orúko nitori eyi, wọn lè fi orúkọ ọmọ pe àgbà tàbi ki wọn lo orúkọ apejuwe (bi Bàbá Èkó, Iyá Ìbàdàn).  Ẹ ṣe à yẹ̀ wò àlàyé àti pi pè ibáṣepọ̀ idilé ni ojú iwé yi.

The Western family is made up of, father, mother and their children but this is not so, as Yoruba family on the other hand is made up of extended family that includes; father, mother, children, half/full brothers/sisters, step children, cousins, aunties, uncles, maternal and paternal grandparents.  Yoruba people love respecting the elders, as a result, uncles and aunties that are older than one’s parents are called ‘Father’ or ‘Mother’ and elders are not called by their names as they are either called by their children’s name or by description (example Lagos Father, Ibadan Mother)  Check the explanation and prononciation below.

Share Button

Originally posted 2015-10-27 22:57:10. Republished by Blog Post Promoter

Òṣèlú Ẹ Gbé Èdè Yorùbá Lárugẹ: Politicians – Promote Yoruba Language

Yoruba, other Nigerian languages on the verge of extinction, Prof Akinwunmi Isola warns - News Sunday

Yoruba, other Nigerian languages on the verge of extinction, Prof Akinwunmi Isola warns

Nínú ìwé ìròyìn “Vanguard”, ti ọjọ́ Àìkú, oṣù kẹta, ọjọ́ , ọdún kẹrinlélógún, Ẹgbaalémétàlá, Olùkọ́ àgbà ti Èdè ati Àṣà, Akínwùnmí Ìṣọ̀lá, kébòsí wípé èdè Yorùbá àti èdè abínibí miran le parun ti a ko bá kíyèsára.  Ìkìlọ̀ yí ṣe ìrànlọ́wọ́ fún akitiyan Olùkọ̀wé yi lati gbé èdè àti Yorùbá ga lórí ẹ̀rọ Ayélujára.

Àwọn Òṣèlú tó yẹ ki wọn gbé èdè ìlú wọn lárugẹ n dá kún pí pa èdè rẹ.  Òṣèlú ilẹ̀ Yorùbá ko fi èdè na ṣe nkankan ni Ilé-òsèlú, wọn o sọ́, wọn ò kọ́, wọn ò ká.  Àwọn Òṣèlú ayé àtijọ́ bi Olóyè Ọbáfẹ́mi Awólówọ̀, Olóyè Ládòkè Akíntọlá, àti bẹ̃bẹ lọ gbé èdè wọn lárugẹ bi ó ti ẹ̀ jẹ́ wípé wọn kàwé wọn gboyè rẹpẹtẹ. Yorùbá ní “Àgbà kì í wà lọ́jà kórí ọmọ tuntun wọ́”.  Ó yẹ ki àwọn àgbà kọ́ ọmọ lédè, kí à si gba àwọn ọmọ wa níyànjú wípé sí sọ èdè abínibí kò dá ìwè kíkà dúró ó fi kún ìmọ̀ ni.  Ó ṣeni lãnu wípé àkàkù ìwé ló pọ̀ laarin ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ, wọn ò gbọ́ èdè Yorùbá wọn ò dẹ̀ tún gbọ́ èdè gẹ̀ẹ́sì.

Yorùbá ní “Ẹ̀bẹ̀ la mbẹ òṣìkà pé kí ó tú ìlú rẹ ṣe”, A bẹ àwọn Òṣèlú́ Ilẹ̀ Yorùbá ni agbègbè Èkìtì, Èkó, Ògùn, Ondó, Ọ̀ṣun àti Ọ̀̀yọ́, lati ṣe òfin mí mú Kíkọ àti Kíkà èdè Yorùbá múlẹ̀ ní gbogbo ilé ìwé, ní pàtàkì ní ilé-ìwé alakọbẹrẹ ilẹ̀ Yorùbá nitori ki èdè Yorùbá ma ba a parẹ́.

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button

Originally posted 2013-03-26 21:44:54. Republished by Blog Post Promoter