Tag Archives: Politicians

Òṣèlú Ẹ Gbé Èdè Yorùbá Lárugẹ: Politicians – Promote Yoruba Language

Yoruba, other Nigerian languages on the verge of extinction, Prof Akinwunmi Isola warns - News Sunday

Yoruba, other Nigerian languages on the verge of extinction, Prof Akinwunmi Isola warns

Nínú ìwé ìròyìn “Vanguard”, ti ọjọ́ Àìkú, oṣù kẹta, ọjọ́ , ọdún kẹrinlélógún, Ẹgbaalémétàlá, Olùkọ́ àgbà ti Èdè ati Àṣà, Akínwùnmí Ìṣọ̀lá, kébòsí wípé èdè Yorùbá àti èdè abínibí miran le parun ti a ko bá kíyèsára.  Ìkìlọ̀ yí ṣe ìrànlọ́wọ́ fún akitiyan Olùkọ̀wé yi lati gbé èdè àti Yorùbá ga lórí ẹ̀rọ Ayélujára.

Àwọn Òṣèlú tó yẹ ki wọn gbé èdè ìlú wọn lárugẹ n dá kún pí pa èdè rẹ.  Òṣèlú ilẹ̀ Yorùbá ko fi èdè na ṣe nkankan ni Ilé-òsèlú, wọn o sọ́, wọn ò kọ́, wọn ò ká.  Àwọn Òṣèlú ayé àtijọ́ bi Olóyè Ọbáfẹ́mi Awólówọ̀, Olóyè Ládòkè Akíntọlá, àti bẹ̃bẹ lọ gbé èdè wọn lárugẹ bi ó ti ẹ̀ jẹ́ wípé wọn kàwé wọn gboyè rẹpẹtẹ. Yorùbá ní “Àgbà kì í wà lọ́jà kórí ọmọ tuntun wọ́”.  Ó yẹ ki àwọn àgbà kọ́ ọmọ lédè, kí à si gba àwọn ọmọ wa níyànjú wípé sí sọ èdè abínibí kò dá ìwè kíkà dúró ó fi kún ìmọ̀ ni.  Ó ṣeni lãnu wípé àkàkù ìwé ló pọ̀ laarin ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ, wọn ò gbọ́ èdè Yorùbá wọn ò dẹ̀ tún gbọ́ èdè gẹ̀ẹ́sì.

Yorùbá ní “Ẹ̀bẹ̀ la mbẹ òṣìkà pé kí ó tú ìlú rẹ ṣe”, A bẹ àwọn Òṣèlú́ Ilẹ̀ Yorùbá ni agbègbè Èkìtì, Èkó, Ògùn, Ondó, Ọ̀ṣun àti Ọ̀̀yọ́, lati ṣe òfin mí mú Kíkọ àti Kíkà èdè Yorùbá múlẹ̀ ní gbogbo ilé ìwé, ní pàtàkì ní ilé-ìwé alakọbẹrẹ ilẹ̀ Yorùbá nitori ki èdè Yorùbá ma ba a parẹ́.

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button

Originally posted 2013-03-26 21:44:54. Republished by Blog Post Promoter

Ìtẹ́lọ́rùn ni Baba Ìwà – Contentment is the Father of Character

Àìní ìtẹ́lọ́rùn ló bí gbogbo ìwà burúkú bi:  irọ́ pípa, olè jíjà, àgbèrè, ojúkòkòrò àti bẹ̃bẹ lọ.

Àìní ìtẹ́lọ́rùn ló wà ni ìdí àwọn Oṣèlú àti Olórí Ìjọ ti o nlo owó ìlú tàbi owó ìjọ fún ara wọn dipò ki wọn lõ fún ìlú àti ìjọ.   Ọ̀pọ̀lọpọ̀ Òṣèlú̀ ilẹ̀ Nigeria á fi ọ̀nà ẹ̀rú wá ipò nítorí àti kó owó ìlú jẹ, wọn ki wúlò fún ìlú ṣùgbọ́n fún ara wọn.  Èyí tó ṣeni lãnu jù ni wípé kò sí owó ti wọn ji tí ó tó, nítorí wípé wọn a ji owó àti ohun ti wọn kò ní lò títí di ọjọ́ ikú àti kó èyí tí wọ́n rò wípé ọmọ wọn kò ní ná tán.

Ibi tí àìní ìtẹ́lọ́rùn burú dé ni orílẹ̀ èdè wa, o ràn àwọn ọ̀pọ̀lọpọ̀ Olórí Ìjọ tí ó yẹ ki o wãsu èrè ìtẹ́lọ́rùn fún àwọn Òṣèlú, ará ìlú àti ọmọ Ìjọ.  Ó ṣeni lãnu wípé ojúkòkòrò ọ̀pọ̀lọpọ̀ Olórí Ìjọ ju ti Òṣèlú, ọmọ Ìjọ àti àwọn ẹlẹ́tàn lọ nítorí wọ́n du ipò àti ohun ayé.

Il̀ú á dára si ti àwọn ènia bá lè mú òwe Yorùbá tí ó wípé “Ìtẹ́lọ́rùn ni Baba Ìwà” yí lò.

ENGLISH TRANSLATION

Lack of contentment is the root cause of bad character like: lying, prostitution, covetousness etc.

Lack of contentment is behind the source of Politicians and Church Leaders embezzling public fund and congregation’s tithes and offering for their own personal use.  Many Nigerian Politicians would use every crooked means to be elected to any position in politics in order to be in a position to have access to public fund and afterward, they are often useless to their electorate but for themselves.  The most pitiable thing is that they steal the money and things they will never need to their dying day as well as storing up what they think their children would never be able to finish.

The worst side of lack of contentment in our country, there is no difference between the Church Leaders who are supposed to be preaching about the reward of contentment to the Politicians, the people and fraudsters.  It is unfortunate that many Church Leaders are more covetous than Politicians, Church Congregants and Fraudsters, as a result of competing for position and mundane things.

The Country will be better off if the Yoruba adage that said “Contentment is the Father of Character” can be applied.

Share Button

Originally posted 2013-06-25 19:40:35. Republished by Blog Post Promoter