Tag Archives: Mariam Yahia Ibrahim

“Ìwà lẹ̀sìn, A ki fi òtítọ́ sinú gbàwìn ìkà”: Ìjọba Sudan dá ẹjọ́ ikú fún Mariam Yahia Ibrahim nitori ẹ̀sin – “Good Character is key to worship”

Sudan Death Sentence Woman Gives Birth In Jail

 

Mariam Yahya Ibrahim

Ìjọba Sudan dá ẹjọ́ ikú fún Mariam Yahia Ibrahim nitori ẹ̀sin – Sudan Death Sentence Woman Gives Birth In Jail

Yorùbá ni “Ọmọ ẹni kò lè burú titi, ká fi fún Ẹkùn pa jẹ”, ki ṣe bi ti obinrin Sudan – Mariam Yahia Ibrahim ti wọn gbé si ẹ̀wọ̀n pẹ̀lú oyún lati dúró de idájọ́ ikú lẹhin ọmọ bibi nitori ẹ̀sìn.  Ohun pẹ̀lú ọmọ ti ó ti bi tẹ́lẹ̀ ni wọn gbé jù si ẹ̀wọ̀n fún ẹ̀sùn pé kò yẹ ki ó fẹ́ ìgbàgbọ́ lábẹ́ òfin “Sharia”.  Lábẹ́ òfin yi, ọkunrin Ìmàle lè fẹ́ obinrin ni ẹ̀sìn miran, ṣùgbọ́n obinrin wọn kò ni ẹ̀tọ́ lati fẹ́ ẹni ti ó bá ṣe ẹ̀sìn miran.

Kò si bi ẹni ti ó fa ọmọ rẹ̀ silẹ̀ nitori ó fẹ́ ẹlẹ́sìn miran ti lè sọ pé ohun ni òtitọ́ ninú gbàwìn ìkà.  Bawo ni enia ṣe lè pa ẹni-keji nitori ẹ̀sìn? Ìkà ti wà ninú irú àwọn bayi ki wọn to gba ẹ̀sìn, wọn kan fi ẹ̀sìn bojú ṣe ìkà ni.  Àjà ni wọn fi ḿbọ̀ Ògún ki ṣe enia.  Yorùbá ni “A ki fi ọmọ Ọrẹ̀, bọ Ọrẹ̀”, òwe yi túmọ̀ si pe abòriṣà Yorùbá kò jẹ́ fa ọmọ rẹ silẹ fún ikú nitori ó yà kúrò ninú ẹ̀sin ibilẹ̀.

Ibrahim has a son, 18-month-old Martin, who is living with her in jail, where she gave birth to a second child last week. By law, children must follow their father's religion

Ohun pẹ̀lú ọmọ ti ó ti bi tẹ́lẹ̀ ni wọn gbé jù si ẹ̀wọ̀n – Meriam Ibrahim with her son and the newborn

Ìròyìn jade pé Mariam Yahia Ibrahim ti bi ọmọ si ẹ̀wọ̀n, a ri ninú ẹbi rẹ ti o ke pe ki won fi ikú si-so pá ti ó bá kọ̀ pé ohun kó padá si ẹ̀sìn Ìmàle.  Gbogbo àgbáyé ḿbẹ̀ àwọn Òṣèlú Sudan ki wọn tú obinrin àti àwọn ọmọ rẹ̀ silẹ̀ nitori irú ẹjọ́ oró yi, kò tọ̀nà ni ayé òde òni.

 

 

 

ENGLISH LANGUAGE Continue reading

Share Button