Nitotọ àti ṣe ẹ̀yà orí tẹlẹ ṣugbọn a lérò wípé orúkọ gbogbo ẹ̀yà ara lati orí dé ẹsẹ á wúlò fún kíkà.
Ẹ̀yà Ara ni Èdè Yorùbá and the English Translation of names of part of the body
Though the names of parts of the head had earlier been published but we think the readers will find the names of the whole body from head to toe will be useful for reading
Ọọni Ifẹ̀ Kọkànlélaadọta gba Adé – Ooni of Ife Oba Enitan Ogunwusi after receiving the AARE Crown from the Olojudo of Ido land on Monday PHOTOS BY Dare Fasub
Ilé-Ifẹ̀ tàbi Ifẹ̀ jẹ ilú àtijọ́ ti Yorùbá kà si orisun Yorùbá. Lẹhin ọjọ mọ́kànlélógún ni Ilofi (Ilé Oyè) nigbati gbogbo ètùtù ti ó yẹ ki Ọba ṣe pari, Ọba Adéyẹyè Ẹniitàn, Ògúnwùsi gba Adé Aàrẹ Oduduwa ni ọjọ́ kẹtàlélógún oṣù kọkànlá ọdún Ẹgbàálemẹ͂dógún ni Òkè Ọra nibiti Bàbá Nlá Yorùbá Oduduwa ti kọ́kọ́ gba adé yi ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún sẹhin.
Ọba Ogunwusi, Ọjaja Keji, di Ọba kọkànlélaadọta Ilé Ifẹ̀, lẹhin ti Ọba Okùnadé Sijúwadé pa ipò dà ni ọjọ́ kejidinlọgbọn, oṣù keje odun Ẹgbàálemẹ͂dógún.
Gẹ́gẹ́ bi àṣà àdáyébá, ẹ͂kan ni ọdún nigba ọdún Ọlọ́jọ́ ti wọn ma nṣe ni oṣù kẹwa ọdún ni Ọba lè dé Adé Aàrẹ Oduduwa.
Ni ayé àtijọ́ ẹsẹ̀ ni gbogbo èrò ma nlo lati rin lati ìlú kan si keji nigbati ọkọ̀ ìgbà̀lódé kò ti wọpọ. Ilé Ọba àti Ìjòyè ni a ti le ri ẹṣin nitori ẹṣin kò lè rin ninu igbó kìjikìji ti o yi ilẹ̀ Yorùbá ká. Ọrọ Yorùbá ayé òde òní ni “Ẹsẹ̀ yá ju mọ́tọ̀ (ọkọ̀) ara lo nfàbọ̀ si”. Ọ̀rọ̀ yi bá àwọn èrò ayé àtijọ́ mu nitori ìrìn-àjò ti wọn fi ẹsẹ̀ rin fún ọgbọ̀n ọjọ́, ko ju bi wákà̀̀tí mẹ́fà lọ fún ọkọ ilẹ̀ tàbi ogoji ìṣẹ́jú fún ọkọ̀-òfúrufú.
Ẹ ṣe àyẹ̀wò àwọn ohun ìrìnsẹ̀ ayé àtijọ́ àti ayé òde òní ni èdè Yorùbá, ohun àti àwòrán ti ó wà ni ojú ewé yi.
ENGLISH TRANSLATION
In the olden days, people move about by walking from one place to the other, this was before the advent of the modern means of transportation. Horses were only found in the Kings and Chief’s house due to the ecology of the Yoruba region which is surrounded by thick forest. According to the modern Yoruba adage “Legs are faster than vehicle wears the body out”. This can be applied to the ancient people because the journey that they had to walk for thirty (30) days is not more than six (6) hours journey in a car or forty (40) minutes by air.
View the slide below on this page for the Yoruba names of means of travelling in the olden and modern times:
Ọdún Kérésì jẹ́ ọdún Onigbàgbọ́ lati ṣe iránti ọjọ́ ibi Jésù Olùgbàlà. Ọjọ́ kẹjọ lẹhin ọdún Kérésìmesì ni ọdún tuntun. Fún ayẹyẹ ọdún, kò si iyàtọ̀ laarin Ìgbàgbọ́ àti Mùsùlùmi ni ilẹ̀ Yorùbá nitori Yorùbá gbà wi pé “Ẹni ọdún bá láyé, ó yẹ kó dúpẹ́”. Ọpẹ́ ló yẹ ki èniyàn dá ju igbèsè ji jẹ lati ṣe àṣe hàn ni àsikò ọdún.
Ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún sẹhin, àwọn Àgbẹ̀ á dari wálé pẹ̀lú irè oko pàtàki iṣu. Àwọn Oniṣòwò á ri ọjà tà nitori àsikò yi ni Bàbá àti Ìyá ma nrán aṣọ ọdún fún àwọn ọmọdé àti oúnjẹ rẹpẹtẹ fún ipalẹ̀mọ́ ọdún. Inú ọmọdé ma ndùn nitori asiko yi ni wọn nse irẹsi àti pa adiẹ fún ọdún. Àwọn ọmọdé á lọ lati ilé ẹbi kan si ekeji, ẹbi ti wọn lọ ki, á fún wọn ni oúnjẹ àti owó ọdún. Àwọn àgbàlagbà naa ma ndá aṣọ ẹgbẹ́ fún idúpẹ́ ọdún, ṣùgbọ́n ki owó epo rọ̀bi tó gba igboro, ki ṣe aṣọ olówó nla bi ti ayé òde òni.
Àsikò ti olè npọ̀ si niyi pàtàki ni ilú Èkó, nitori ọ̀pọ̀lọpọ̀ fẹ na owó ti wọn kò ni lati ṣe ọdún. Ìpolówó ọjà pọ̀ ni àsikò yi ni Òkè-Òkun, nitori eyi, ọ̀pọ̀ nlo ike-igbèsè tàbi ki wọn ya owó-èlè lati ra ọjà ti wọn kò ni owó rẹ. Lẹhin ọdún, wọn a fi ọdún tuntun bẹ̀rẹ̀ si san igbèsè, nitori eyi Ìyá àti Bàbá a ma a ti ibi iṣẹ́ kan lọ si ekeji lai ni ìsimi tàbi ri àyè àti bójú tó àwọn ọmọ.
Ọ̀rọ̀ Yorùbá sọ wi pé “Ṣe bi o ti mọ ki i tẹ́ ”, nitori eyi gbogbo ọmọ Yorùbá ni ilé, ni oko, ẹ ṣe bi ẹ ti mọ, ẹ ma tori odun na ọwọ́ si nkan ti ọwọ́ yin kò tó, ki ẹ ma ba a tẹ́. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ Onigbàgbọ́ ayé òde oni ki i fẹ fi èdè Yorùbá kọrin ṣùgbọ́n ẹ gbọ́ bi ọmọ Òyinbó ti kọ orin àwọn “Obinrin Rere” ni ojú iwé yi.
Kò si oye ọdún ti ọ̀pọ̀lọpọ̀ Òṣèlú Ilẹ̀ Aláwọ̀-dúdú lè lò ni ipò ti wọn lè gbà lẹ́rọ̀ lati kúrò. Bi àyè bá gbà wọn, wọn fẹ kú si ori oyè. Bi a bá ṣe akiyesi ọ̀pọ̀lọpọ̀ Òṣèlú Òkè-Òkun, bi àwọn ará ilú bá ti dibò pé wọn kò fẹ́ wọn nipa yin yan ẹlòmíràn, wọn yio gbà lẹ́rọ̀, lati gbé Ìjọba fún ẹni tuntun ti ará ilú yan, ṣùgbọ́n kò ri bẹ ẹ ni Ilẹ̀ Aláwọ̀-dúdú.
Ohun ti ó jẹ́ ki àwọn Òṣèlú Ilẹ̀ Aláwọ̀-dúdú fẹ́ kú si ipò pọ. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ Olóri Òṣèlú Nigeria, ki ba jẹ ti Ìjọba Ológun tàbi Alágbádá, kò si ẹni tó mọ bàbá wọn ni ilú, ṣùgbọ́n wọn kò kọ́ ọgbọ́n pé ọ̀pọ̀ ọmọ ti wọn mọ bàbá wọn ni àwùjọ kò dé ipó nla ti àwọn dé. Ó ṣe é ṣe ki ó jẹ́ wipé ìbẹ̀rù iṣẹ́ ti ó ṣẹ́ wọn ni kékeré ló jẹ́ ki wọn ni ojúkòkòrò lati fi ipò wọn ji owó ilú pamọ́ fún ara wọn, ọmọ àti aya wọn nitori ìbẹ̀rù iṣẹ́. Kò si oye owó ti wọn ji pamọ́ ti ó lè tẹ́ wọn lọ́rùn, eyi ló fa ìbẹ̀rù à ti kúrò ni ipò agbára. Ìbẹ̀rù ki ẹni ti ó bá má a gba ipò lọ́wọ́ wọn, ma ṣe ṣe iwadi wọn na a pẹ̀lú, nitori wọn ò mọ̀ bóyá yio bá wọn ṣe ẹjọ́ lati gba owó ilú ti wọn ji kó padà.
Kàkà ki ilú gbérí, ṣe ni ọlá ilú nrẹ̀hìn. Bi Òsèlú bá ji owó, wọn a ko ọ̀pọ̀ owó bẹ́ ẹ̀ lọ si Òkè-Òkun tàbi ki wọn ri irú owó bẹ́ ẹ̀ mọ́lẹ̀ lóri ki kọ ilé ọ̀kẹ́ aimoye ti ẹni kan kò gbé. Ọ̀pọ̀ owó epo-rọ̀bì ló wọlé, ṣùgbọ́n àwọn Òṣèlú àti àwọn olè bi ti wọn njẹ ìgbádùn nigbati ará ilú njìyà. Lára ìpalára ti ji ja ilú ni olè fa, ni owó Nigeria (Naira) ti ó di yẹpẹrẹ, àwọn ọdọ kò ri iṣẹ́ ṣe, àwọn ohun amáyé-dẹrùn ti bàjẹ́ tán, oúnjẹ wọn gógó àti bẹ́ ẹ̀ bẹ́ ẹ̀ lọ.
Òwe Yorùbá ti ó ni “Ohun gbogbo ki i tó olè” fi àlébù ojúkòkòrò, ifẹ́ owó, àti à ṣi lò agbára han ni ilú, pàtàki ni Nigeria.
Kòró/Kòrọ́nà – Ogun ti a kò rí: Coronavirus – the invisible war
Àjàkálẹ̀ àrùn ma ńṣẹlẹ̀ láti ìgbà-dé-ìgbà. Ni igba kan ri, àjàkálẹ̀ àrùn bi Ṣọ̀pọ̀ná/Olóde, Ikọ́-ife, Onígbáméjì àti bẹ́ẹ̀ bẹ́ẹ̀ lọ, ló kári ayé. Ni ọdún kẹtàlélógòji sẹhin, Ìkójọ Ètò-Ìlera Àgbáyé (WHO) ṣe ikéde òpin àrùn Ṣọ̀pọ̀ná/Olóde. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn àjàkálẹ̀ àrùn àgbáyé yi, kò jà ju ọdún kan lọ, nigbati àwọn àjàkálẹ̀ àrùn àgbáyé miràn ṣi wa titi di àsikò yi. Àrùn Ikọ́-ife kò ti tán pátápátá ni àgbáyé nigbati àrùn Onígbá-meji ti kásẹ̀ ni Òkè-Òkun ṣùgbọ́n kò ti kásè kúrò ni àwọn orilẹ̀-èdè miràn.
Ni igbà ogun àgbáyé, wọn kò ṣe òfin onílé-gbélé. Ẹni ti àjàkálẹ̀ àrùn bi Ṣọ̀pọ̀ná/Olóde tabi Ikọ́-ife, ba nse ni wọn ńsé mọ́lé, ki ṣe gbogbo ilú. Ninu itan, ko ti si àjàkálẹ̀ àrùn ti o se gbogbo agbaye mọle bi ti eyi ti ó njà lọ́wọ́lọ́wọ́, ti Yorùbá sọ ni “Kòró” yi, nitori olóko kò lè re oko, ọlọ́jà kò lè re ọjà, oníṣẹ́-ọwọ́ tàbi oníṣẹ́ ìjọba, omo ilé-ìwé àti bẹ́ ẹ̀ bẹ́ ẹ̀ lọ wà ni àhámọ́. Àwọn Onímọ̀-ijinlẹ ṣe àkíyèsí pé inú afẹ́fẹ́ ni àrùn yi ńgbé, o si ńtàn ni wéré-wéré ni ibi ti ọ̀pọ̀ ènìyàn bá péjọ si. Ìjọba ṣe òfin “onílé-gbélé” ti kò gba àpèjọ ti ó bá ju èniyàn mẹwa lọ, èniyàn mẹwa yi ni lati fi ẹsẹ̀ bàtà mẹfa si àárin ẹni kan si èkeji, èyi ni kò jẹ́ ki ẹlẹ́sin Jesu àti Mùsùlùmi péjọ fún ìjọsin ni ọjọ́ ìsimi tàbi ọjọ́ Ẹti. Ọmọ lẹhin Jesu ko le péjọ lati ṣe ikan ninu ọdún ti ó ṣe pàtàki jù fún Ọmọ lẹhin Jesu, ọdún Ajinde ti ọdún Ẹgbàálélógún, Àrùn yi ti mú ẹgbẹgbẹ̀rún ẹmi lọ, o si ti ba ọrọ̀-ajé jẹ́ fún gbogbo orilè-èdè àgbáyé.
Ki Ọlọrun sọ “kòró” di kòrọ́nà gbe gbà lai pẹ́. Àwọn Onímọ̀-ìjìnlẹ̀, Oníṣègùn àti àwọn alabojuto-aláìsàn ńṣe iṣẹ́ ribiribi lati dojú ìjà kọ arun “kòró”. Ninu ìtàn àjàkálẹ̀ àrùn àgbáyé nigbati ko ti si abẹ́rẹ́ àjẹsára, a ṣe àkíyèsí pé àwọn iṣọ́ra ti wọn ṣe wọnyi wúlò lati gbógun ti àrùn Kòró.
Ànìkàngbé/Àdádó – Isolation Àhámọ́ – Quarantine Ìmọ́tótó – Good personal hygiene such regular washing of hands Li lo egbogi-apakòkòrò – Using disinfectants Onílégbélé/Dín àpéjọ kù – Stay Home/Avoid large gathering Bi bo imú àti ẹnu – Wearing mask
ENGLISH TRANSLATION
Pandemic is not new in the world, as it occurs from time-to-time. Smallpox, Tuberculosis, cholera Etc. were once upon a time a pandemic ravaging the world. The World Health Organization declared the eradication of Smallpox on December 9, 1979. Tuberculosis has not been completely eradicated while Cholera has been drastically contained in the developed world with some cases still occurring in the developing world. Continue reading →
Originally posted 2020-04-16 01:09:11. Republished by Blog Post Promoter
Yorùbá ni ètò àti òfin ti àwọn Àgbà, Ọba àti Ìjòyè fi nto ilú ki aláwọ̀-funfun tó dé. Onirúurú ọ̀nà ni wọn ma fi nṣe idájọ́ ìkà laarin àwùjọ. Wọn lè fi orin tú àṣiri òṣìkà ni igbà ọdún ibilẹ, tàbi ki wọn fa irú ẹni bẹ ẹ si iwájú Àgbà idilé, Baálẹ̀ tàbi Ọba fún ìdájọ́ ti ó bá tọ́ si irú ẹni bẹ ẹ. Lati agbo ilé dé ilé iwé àti àwùjọ ni Yorùbá ti ma nlo òwe, ọ̀rọ̀ àti orin ṣe ikilọ fún ọmọdé àti àgbà pé ẹ̀san wà fún oniṣẹ ibi tàbi òṣìkà.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ Eléré àti Olórin, pàtàki àwọn Ọ̀gá ninú Eléré àti Olórin Yorùbá ni ó fi ẹ̀san òsìkà hàn ninú eré àti orin. Ọ̀gá Eléré bi: Lere Paimọ, Olóògbe Kọla Ogunmọla, Olóògbe, Oloye Ogunde àti ọpọ ti a kò dárúkọ, àti àwọn ọ̀gá Olórin bi: Olóògbé, Olóyè I.K. Dairo, Oloogbe Adeolu Akinsanya (Baba Ètò), Olóyè (Olùdari) Ebenezer Obey, Olóògbe Orlando Owoh, Dele Ojo, Olóògbe Sikiru Ahinde Barrister àti ọ̀pọ̀ ti a kò dárúkọ nitori àyè. Ẹ gbọ́ ikan ninú àwọn orin ikilọ fún òsìkà ti àwọn ọmọ ilé-iwé ma nkọ ni ojú ewé yi bi Olùkọ̀wé yi ti kọ:
Ṣìkà-ṣìkà gbàgbé àjọbí Adániloró gbàgbé ọ̀la Ẹ̀san á ké, á ké o Ẹ̀san á ké lorí òsìkà Ṣe rere ò, ko tó lọ ò.
Oriṣiriṣi wèrè ló wà, nitori pé ki ṣe wèrè ti ó wọ àkísà ni ìgboro tàbi já sita nikan ni wèrè. Ẹnikẹni ti o nhu ìwà burúkú tàbi ṣe ìpinnu burúkú ni Yorùbá npè ni “wèrè”.
Wèrè – Mad person
Ìpinnu ṣi ṣe, ṣe pàtàki ni ayé àtijọ́ àti òde òní. Òwe Yorùbá sọ wi pé “Bi ará ilé ẹni bá njẹ kòkòrò búburú, hẹ̀rẹ̀-huru rẹ̀ kò ni jẹ́ ki a sùn ni òru”. Àbáyọrí ìpinnu tàbi èrò burúkú kò pin si ọ̀dọ̀ ẹbi àwọn ti ó wà ni àyíká elérò burúkú, ó lè kan gbogbo àgbáyé. Fún àpẹrẹ, kò si ìyàtọ̀ laarin wèrè tó já sita nitori wèrè ni Yorùbá npe ọkọ tàbi ìyàwó ti ó ni ìwà burúkú, ẹbi burúkú, ọba ti ó nlo ipò rẹ lati rẹ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ jẹ àti òṣèlu ti ó nja ilú ni olè lati kó owó ti wọn ji lọ si òkè òkun nibiti ohun amáyédẹrùn ti ilú wọn kò ni wà.
Gẹ́gẹ́ bi òwe Yoruba ti ó sọ wi pé “A ki sọ pé ki Wèrè ṣe òkú ìyá rẹ̀ bi ó bá ṣe ri, bi ó bá ni òhun fẹ́ sún jẹ nkọ́?” Ìtumọ̀ òwe yi ni wi pé ìpinnu pàtàki bi ìyè àti ikú kò ṣe é gbé lé wèrè lọ́wọ́. Ó yẹ ki àwọn ènìyàn gidi ti ori rẹ pé dásí ọkọ tàbi ìyàwó, ọba tàbi àwọn ti ó wà ni ipò agbára, òṣèlu ti o nfi ipò wọn jalè àti àwọn ti ó nhu ìwà burúkú yi lati din àbáyọrí ìwà burúkú lóri ẹbí, alá-dúgbò àti àgbáyé kù.
Èkó jẹ́ olú ìlú Nigeria fún ọpọlọpọ ọdún, ki wọn tó sọ Abuja di olú ìlú Nigeria, ṣùgbọ́n Èkó ṣi jẹ́ olú ìlú fún iṣẹ ọrọ̀ gbogbo Nigeria. Nitori eyi, gbogbo ẹ̀yà Nigeria àti àwọn ará ìlú miran titi dé òkè-òkun/ìlú-òyinbó ló wà ni Èkó.
Yorùbá ni èdè ti wọn nsọ ni ìgboro Èkó, ṣùgbọ́n ọpọlọpọ gbọ èdè Gẹẹsi, pataki àwọn ti ki ṣé ọmọ Yorùbá. Ẹ wo díẹ̀ ni àwọn ìṣe àti ọ̀rọ̀ ni ìgboro Èkó:
ENGLISH TRANSLATION
Lagos was the capital of Nigeria for many years before the capital was moved to Abuja, but Lagos remains the commercial capital of Nigeria. As a result, every ethnic group in Nigeria and people from abroad/Europe are present in Lagos.
Ni aiyé àtijọ́, ẹsin àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ló dàbi ọkọ̀ igbàlódé ti wọn ńpè ni mọ́tò. Ẹni ti ó jẹ́ ọlọ́rọ̀, ló lè ni ẹsin tàbi kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Ẹsẹ̀ ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ fi ńrin irin àjò.
Ìtàn yi dá ló̀ri Bàbá àti ọmọ rẹ ti wọn ńsin kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Wọn múra lati rin irin àjò. Gẹ́gẹ́ bi àṣà Yorùbá lati bu ọ̀wọ̀ fún àgbà, Bàbá ló gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ọmọ rẹ bẹ̀rẹ̀ si rin tẹ̀lé kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Àwọn enia ti o ri wọn ni “Bàbá, iwọ gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ọmọ ńrin ni ilẹ̀”. Nitori ọ̀rọ̀ yi, Bàbá bọ́ silẹ̀, ó gbé ọmọ rẹ gun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Àwọn aiyé tún ri wọn ni “Bàbá ńrin nilẹ̀, ọmọ ńgun kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́”. kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn ti dàgbà, ṣùgbọ́n tori ẹnu aiyé, Bàbá àti ọmọ bá mú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ gùn. Wọn ko ti rin jinà nigbati àwọn ti ó ri wọn tún ni “Ẹ wo Bàbá àti ọmọ tó fẹ́ pa kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́”. Nitori àti tẹ́ aiyé lọ́run, Bàbá àti ọmọ bọ́ silẹ̀, wọn bẹ̀rẹ̀ si fi ẹsẹ̀ rin tẹ̀lé kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Àwọn arin irin àjò yókù tún ri wọn, wọn ni “Ẹrú aiyé ni àwọn eleyi, bawo ni wọn ṣe lè ni kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, ki wọn ma fi ẹsẹ̀ rin?”
Nigbati Bàbá ti gbìyànjú titi, ti kò mọ ohun ti ó tún lè ṣe mọ́, lati tẹ́ aiyé lọ́rùn ni ó ránti ọ̀rọ̀ Yorùbá tó ni “Kò si ọgbọ́n ti o lè dá, kò si iwà ti o lè hù, ti o lè fi tẹ́ aiyé lọ́rùn”.
Yorùbá ni “Ẹni à ḿbá ra ọjà là ńwò, a ki wó ariwo ọjà̀”. Lára nkan ti itàn yi kọ́ wa ni pé: ohun ani là ńlò; ibi ti à ńlọ ni ká dojú kọ lai wo ariwo ọjà àti pé enia ni lati ni ọkàn tirẹ̀ nitori kò si ẹni ti ó lè tẹ́ aiyé lọ́rùn.
Ẹ gbọ bi ògúná gbòngbò ninú àwọn ọ̀gá ninú olórin ilẹ̀ Yorùbá àti ilẹ̀ aláwọ̀ dúdú – “Chief Ebenezer Fabiyi” ti a mọ si “Olóyè Adarí” ti fi itàn yi kọrin.
Originally posted 2014-04-15 22:41:38. Republished by Blog Post Promoter
This website uses cookies to improve your experience. We'll assume you're ok with this, but you can opt-out if you wish. Cookie settingsACCEPT
Privacy & Cookies Policy
Privacy Overview
This website uses cookies to improve your experience while you navigate through the website. Out of these cookies, the cookies that are categorized as necessary are stored on your browser as they are essential for the working of basic functionalities of the website. We also use third-party cookies that help us analyze and understand how you use this website. These cookies will be stored in your browser only with your consent. You also have the option to opt-out of these cookies. But opting out of some of these cookies may have an effect on your browsing experience.
Necessary cookies are absolutely essential for the website to function properly. This category only includes cookies that ensures basic functionalities and security features of the website. These cookies do not store any personal information.
Any cookies that may not be particularly necessary for the website to function and is used specifically to collect user personal data via analytics, ads, other embedded contents are termed as non-necessary cookies. It is mandatory to procure user consent prior to running these cookies on your website.