Ìṣe Ilé ló mbá ni dode – Trudy Alli-Balogun ja Ilé-Iṣẹ́ rẹ lólè – The character cultivated at home often reflect in the public – Trudy Alli-Balogun a Council Officer jailed for £2.4 million housing fraud

Ìbá ṣe pọ̀ laarin Yorùbá àti Ìlú-Ọba ti lé ni igba ọdún nitori òwò Òkè-òkun, pàtàki òwò ẹrú àti fún ẹ̀kọ́ ni ilé iwé giga.  Nitori eyi, àṣà àti èdè Yorùbá kò ṣe fi ọwọ́ rọ sẹhin.

fraud.jpg

Trudy Alli-Balogun jailed for 5 years over £2.4 million housing fraud

Ni Ilú-Ọba, ẹ̀tọ́ ará ilú ni ki Ìjọba pèsè ohun amáyédẹrùn, pàtàki ibùgbé fún ọmọ ilú, ilé-ìwòsàn ọ̀fẹ́ fún ọmọ àti ará ilú.  Àwọn ẹ̀tọ́ wọnyi kò tọ́ si àlejò, ẹni ti ó fi èrú wọ ilú ti kò ni àṣẹ igbelu, tàbi ẹni tó ni iwé lati ṣe iṣẹ ṣùgbọ́n ko ti i di ará ilú.  Ẹni ti ó ni iwé-igbelu lati ṣe iṣẹ́ ti ko ti di ará ilú kò ni ẹ̀tọ́ si ilé Ìjọba, ṣùgbọ́n wọn ni ẹ̀tọ́ si ilé-ìwòsàn ọ̀fẹ́. Iwé ìròyìn irọlẹ, gbe jade bi Trudy Alli-Balogun, ti lo ipò rẹ ni ilé iṣẹ́ ti ó nṣe ipèsè ibùgbé fún ọmọ ilú, lati gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ lọ́wọ́ àwọn Yorùbá ti kò ni ẹ̀tọ́ si irú ilé bẹ́ ẹ̀.  Wọn ṣe ìdájọ́ ẹ̀wọ̀n ọdún marun fún.

Ìròyìn ti ó gbòde ni inu iwé ìròyìn  àti lori ayélujára fi han bi àwọn Olóri Òṣèlú, Aṣòfin àgbà nla àti kékeré, òṣiṣẹ́ Ìjọba àgbà àti àwọn ti ó wà ni ipó giga ni Nigeria ti lo ipò wọn lati fi ja ilu lólè.  Àyipadà ni Ìjọba pẹ̀lú pe Olóri Òṣèlú Muhammadu Buhari/Yẹmi Osinbajo ti ó gbógun ti iwà ibàjẹ́, ló jẹ ki àṣiri iṣẹ́ ibi wọnyi jade si ará ilú bi àwọn ti ó  wà ni ipò giga ti nlo ipò lati fi hu iwà ibàjẹ́ nitori àti kó ọrọ̀ jọ ni ọ̀nà ẹ̀bùrú.

Yorùbá sọ wi pé “Ìṣe ilé ló mbá ni dode”.  Ni àtijọ́, àṣà Yorùbá ni lati wá idi bi enia ti kó ọrọ̀ jọ, ṣùgbọ́n ni ayé òde oni, olówó ni wọ́n mbọ, bi ó bá ti ẹ jalè tàbi ti ẹ̀wọ̀n de nitori iṣẹ́ ibi.  Àyipadà burúkú yi ni obìnirin Trudy Alli-Balogun gbé dé ẹnu iṣẹ́ lati ja ilé iṣẹ́ rẹ ni olè ọ̀kẹ́ aimoye, ti ó si na owó bẹ́ ẹ̀ ni ìná àpà lai ronú orúkọ burúkú ti ó rà fún Yorùbá àti gbogbo orilẹ̀ èdè Nigeria ni Ilú-Ọba àti pé irú iwà ibàjẹ́ yi ló ba ohun amáyédẹrùn jẹ ni Nigeria.  Iwà ibàjẹ́ kò ni orúkọ meji, ẹni ba jalè ba ọmọ jẹ́.

ENGLISH TRANSLATION

The relationship between the Yoruba people with the United Kingdom dated over two hundred years as a result of trans-Atlantic trade, slave trade and coming to acquire higher education.

In the United Kingdom, it is the right of the citizens and residents to be provided with modern infrastructure such as public housing and free health care.  However, visitors, illegal immigrant, non-permanent residents are not entitled to any benefit.  Those with work permit are not entitled to public housing but are entitled to free health care.  As published in the Evening Standard of Thursday, May 5, 2016, Trudy Alli-Balogun used her position as Southwark Council Housing Officer in London to defraud the Council to the tune of £2.4 million by allocating Council houses to her Yoruba cronies who are not entitled, hence has been jailed for five years.

The news making the round in the papers and on line revealed how the Political Leaders, Senators, Members of House of Assembly, Heads of Government Offices and those in high position of authority has used their position of authority to defraud Nigeria over time.  The change of Government that ushered in President Muhammadu Buhari/Yemi Osinbajo that declared a war on corruption, led to the revelation how Nigerian leaders has used their position to amass public fund to themselves.

According to Yoruba proverb “The character cultivated at home often reflect in the public”.  In time past, Yoruba people often inquire about the source of people’s wealth unlike nowadays, when people are worshipping those who acquired wealth through fraudulent means or have just returned from prison.  The recent change of Government in Nigeria that ushered in President Muhammadu Buhari/Yemi Osinbajo and their stance on corruption has exposed how people in position of authority in Nigeria have enriched themselves through corrupt means at the expense of provision of infrastructure.  Corruption has no other name and should be condemned as thieves has brought upon themselves shame.

Share Button

Originally posted 2016-05-06 23:39:56. Republished by Blog Post Promoter

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

Time limit is exhausted. Please reload the CAPTCHA.