Category Archives: Yoruba Community

Ìkà ò jẹ́ ṣe ọmọ ẹ bẹ́ẹ̀ – Gbi gba wèrè mọ ẹ̀sìn Aláwọ̀-dúdú: The wicked always protect their own – Religious madness in Africa

Libya migrants: Muslim refugees arrested in Italy for throwing Christians into sea after fight

Libya migrants: Muslim refugees arrested in Italy for throwing Christians into sea after fight

Ni ọjọ́ kẹrin-din-lógún, oṣ̀u kẹrin ọdún Ẹgbãlemẹdógún, ọwọ́ Ọlọpa Italy tẹ ọkunrin mẹ̃dogun ti ó ju àwọn Ìgbàgbọ́ mejila si odò nitori ẹ̀sìn lati inú ọkọ̀ ojú agbami ti o nko Aláwọ̀-dúdú ti ó nsa fún ogun àti iṣẹ lo si Òkè-òkun/Ilú-Òyinbò.

Ni gbogbo ọ̀nà ni Aláwọ̀-dúdú fi gba wèrè mọ́ ẹ̀sìn.  Lára gbi gba wèrè mọ́ ẹ̀sìn ni Àlùfã fi ni ki àwọn ọmọ ijọ bẹ̀rẹ̀ si jẹ koríko ti ọmọ rẹ kò lè jẹ, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ijọ ti ó jẹ koríko ló gba wèrè mọ́ ẹ̀sìn.  Ọmọ ijọ ti kò le bọ ara rẹ tàbi bọ ọmọ, ti ó nda ida-mẹwa nigbati Olóri Ijọ nfi owó yi gun ọkọ̀ òfúrufú fi han pé ọ̀pọ̀ ti gba wèrè mọ́ ẹ̀sìn.  Aládurà ti ó nri iran ti kò ri tara rẹ gba wèrè mọ́ ẹ̀sìn.

A screen capture from a Boko Haram video purporting to show the kidnapped girls

‘The Chibok girls are never being freed,’ says Boko Haram leader

Ẹlẹ́sin Mùsùlùmi ti ó npa ẹlòmíràn ni orúkọ ẹ̀sìn gba wèrè mọ́ ẹ̀sìn.  Eyi ti ó ni èèwọ̀ ni iwé kika fún ẹ̀sìn ohun “Boko Haram” ti wọn fi nba ilé iwé jẹ, ji àwọn obinrin kò kúrò ni ilé iwé, fihàn pé wọn gba wèrè mọ́ ẹ̀sìn.  Ọjọ́ kẹrinla oṣù kẹrin ọdún Ẹgbãlemẹdógún ló pé ọdún kan ti ẹgbẹ́ burúkú “Boko Haram” ti ko igba-le-mọkandinlógún obinrin kúrò ni ilé-iwè ni Chibok.  Lèmọ́mù rán ọmọ tirẹ̀ lọ si ilé-iwé, irú àwọn ọmọ Lèmọ́mù ti ó ka iwé ni ó nṣe Òṣèlú tàbi jẹ ọ̀gá ni iṣẹ́ Ìjọba.

Kò si Òṣèlú Aláwọ̀-dúdú ti kò sọ pé ohun jẹ Onígbàgbọ́ tàbi Mùsùlùmi ṣùgbọ́n eyi kò ni ki wọn ma ja ilú ni olè.  Ìfẹ́ agbára ki jẹ ki wọn fẹ gbe ipò silẹ̀ nitori eyi wọn á fi ẹ̀sìn da ilú rú.  Eleyi ló fa ogun ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ilẹ̀ Aláwọ̀-dúdú. Continue reading

Share Button

Originally posted 2015-04-18 00:30:26. Republished by Blog Post Promoter

“A ngba òròmọ adìẹ lọ́wọ́ ikú, ó ni wọn ò jẹ́ ki ohun lọ ààtàn lọ jẹ̀: Ìkìlọ̀ fún àwọn tó fẹ́ lọ Ò̀kè-òkun tipátipá” – “Struggling to save the chicks from untimely death and its complaining of being prevented from foraging at the dump – Caution against desperate illegal Oversea migration”

A lè lo òwe yi lati ṣe ikilọ̀ fún ẹni tó fẹ́ lọ si Òkè-òkun (Ìlu Òyìnbó) lọ́nà kọ́nà lai ni àṣẹ tàbi iwé ìrìnà.  Bi ẹbi, ọ̀rẹ́ tàbi ojúlùmọ̀ tó mọ ewu tó wà ninú igbésẹ̀ bẹ ẹ bá ngba irú ẹni bẹ niyànjú, a ma binú pé wọn kò fẹ́ ki ohun ṣoriire.

Watch this video

More than 3,000 migrants died this year trying to cross by boat into Europe

An Italian navy motorboat approaches a boat of migrants in the Mediterranean Sea

Thirty dead bodies found on migrant boat bound for Italy

Bi oúnjẹ ti pọ̀ tó ni ààtàn fún òròmọ adìẹ bẹni ewu pọ̀ tó, nitori ààtàn ni Àṣá ti ó fẹ́ gbé adìẹ pọ si.  Bi ọ̀nà àti ṣoriire ti pọ̀ tó ni Òkè-òkun bẹni ewu àti ìbànújẹ́ pọ̀ tó fún ẹni ti kò ni àṣẹ/iwé ìrìnà.  Ọ̀pọ̀lọpọ̀ nkú sọ́nà, ọ̀pọ̀ ndé ọhun lai ri iṣẹ́, lai ri ibi gbé tàbi lai ribi pamọ́ si fún Òfin nitori eyi, ọ̀pọ̀ wa ni ẹwọn. Lati padà si ilé á di ìṣòro, iwájú kò ni ṣe é lọ, ẹhin kò ni ṣe padà si, nitori ọ̀pọ̀ ninú wọn ti ju iṣẹ́ gidi silẹ̀, òmiràn ti ta ilé àti gbogbo ohun ìní lati lọ Òkè-òkun. Bi irú ẹni bẹ́ ẹ̀ ṣe npẹ si ni Òkè-òkun bẹni ìtìjú àti padà sílé ṣe npọ̀ si.

Òwe Yorùbá ti ó sọ pé “A ngba òròmọ adìẹ lọ́wọ́ ikú, ó ni wọn ò jẹ́ ki ohun lọ ààtàn lọ jẹ̀ yi kọ́wa pé ká má kọ etí ikún si ikilọ̀, ká gbé ọ̀rọ̀ iyànjú yẹ̀wò, ki á bà le ṣe nkan lọ́nà tótọ́.

ENGLISH TRANSLATION

This proverb can be applied to someone struggling at all cost to migrate Abroad/Oversea without a Visa or proper documentation.   Even when family, friend or colleague that knows the danger in illegal migration, tries to warn such person of the danger, he/she will be angry of being prevented from prosperity. Continue reading

Share Button

Originally posted 2014-12-19 09:10:15. Republished by Blog Post Promoter

“Àgbá òfìfo ló ńdún woro-woro” – “Empty barrel makes most noise”

Àgbá ti ó kún fún epo-rọ̀bì – Barrel full of Crude oil

Àgbá ti ó kún fún epo-rọ̀bì – Barrel full of Crude oil

Àgbá ti ó kún fún ohun ti ó wúlò bi epo-rọ̀bì, epo-pupa, epo-òróró, epo-oyinbo, ọ̀dà àti bẹ́ẹ̀bẹ́ẹ̀ lọ ki pariwo.  Àgbá òfìfo, kò ni nkan ninú tàbi o ni nkan díẹ̀, irú àgbá yi bi o ti wù ki ó lẹ́wà tó, ni ariwo rẹ máa ńpọ̀ ti wọn ba yi lóri afárá tàbi ori titi ọlọ́dà.

Oil-Barrels-2619620

Àgbá òfìfo ti ó lẹ́wà – Colourful empty barrels

Àgbá òfìfo ni àwọn ti ó wà ni òkè-òkun/ilú òyìnbó ti ó jẹ igbèsè tàbi fi èrú kó ọrọ̀ jọ lati wá ṣe àṣehàn ti wọn bá ti àjò bọ, ohun ti wọn kò tó wọn a pariwo pé àwọn jù bẹ́ẹ̀ lọ.  Ni tòótọ́, ìyàtọ̀ òkè-òkun/ilú-òyìnbó si ilẹ̀ Yorùbá ni pé, àti ọlọ́rọ̀ àti aláìní ló ni ohun amáyé-dẹrùn bi omi, iná mọ̀nà-mọ́ná, titi ọlọ́dà, ilé-iwé gidi, igboro ti ó mọ́ àti bẹ́ẹ̀bẹ́ẹ̀ lọ.  Àwọn Òṣèlú kò kọjá òfin, bẹni irònú wọn ki ṣe ki á di Òṣèlú lati kó owó ilú jẹ.

Ni ayé àtijọ́ ni ilẹ̀ Yorùbá, owó kọ́ ni wọn fi ńmọ ẹni gidi, àpọ́nlé/ọ̀wọ̀ wà fún àgbà, ẹni ti ó bá kàwé, olootọ enia, ẹni tó tẹpá mọ́ṣẹ́,  akin-kanjú àti ẹni ti ó ni òye.  Ni ayé òde òni, àgbá òfìfo ti pọ ninú ará ilú, àwọn Òṣèlú àti àwọn òṣiṣẹ́ ijọba.  Bi wọn bá ti ri owó ni ọ̀nà èrú, wọn a lọ si òkè-òkun/ilú-òyìnbó lati ṣe àṣehàn si àwọn ti wọn bá lọhun lati yangàn pẹ̀lú ogún ilé ti wọn kọ́ lai yáwó, ọkọ̀ mẹwa ti wọn ni, ọmọ-ọ̀dọ̀ ti wọn ni àti ayé ijẹkújẹ ti wọn ńjẹ ni ilé.  Wọn á ni àwọn kò lè gbé òkè-òkun/ilú-òyìnbó, ṣùgbọ́n bi àisàn bá dé, wọn á mọ ọ̀nà òkè-òkun/ilú-òyìnbó fún iwòsàn àti lati jẹ ìgbádùn ohun amáyé-derùn miran ti wọn ti fi èrú bàjẹ́ ni ilú tiwọn.

Bi àgbá ti ó ni ohun ti ó wúlò ninú, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹni gidi tó ṣe àṣe yọri ki pariwo. Ọ̀rọ̀ Yorùbá ti ó ni “Àgbá òfìfo ló ńdún woro-woro”, bá ẹni-kẹ́ni ti ó bá ńṣe àṣehàn tàbi gbéraga wi pé ki wọn yé pariwo ẹnu.

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button

Originally posted 2014-08-08 18:20:28. Republished by Blog Post Promoter

Ìbà Àkọ́dá – Reverence to the First Being

Obinrin ti ó́ nṣe Ì̀bà Aṣẹ̀dá - A woman paying reverence to the Creator. Courtesy: @theyorubablog

Obinrin ti ó́ nṣe Ì̀bà Aṣẹ̀dá – A woman paying reverence to the Creator. Courtesy: @theyorubablog

Ìbà Àkọ́dá, ìbà Aṣẹ̀dá
Ìbà ni n ó f’òní jú, mo r’íbà, k’íbà ṣẹ
Nínú ríríjẹ, nínú àìríjẹ
Mo wá gbégbá ọpẹ́, mo r’íbà k’íbà ṣẹ
Alápáńlá tó so’lé ayé ró
Ṣe àtúntò ayé mi
Ní gbogbo ọ̀nà tí mo ti k’etí ikún sí Ọ
Baba d’áríjì, mo bẹ̀bẹ̀
Odò Orisun Rẹ ni mí, máṣe jẹ́ n gbẹ

Ìbà! ìbà!!

Ọmọ ìkà ń d’àgbà, ọmọ ìkà ń gbèrú
Ọmọ ẹni ire a má a tọrọ jẹ
Ọmọ onínúure a má a pọ́njú
Bó ti wù Ọ ́lo ń ṣ’ọlá Rẹ
Ìṣe Rẹ, Ìwọ ló yé o; Ògo Rẹ, é dibàjẹ́
Àpáta ayérayé, mo sá di Ọ ́o
Yọ́yọ́ l’ẹnu ayé
Aráyé ń sọ Ọ ́sí láburú, aráyé ń sọ Ọ ́sí rere
Ọlọ́jọ́ ń ka’jọ́
Bó pẹ́, bó yá, ohun ayé á b’áyé lọ

Ìbà! ìbà!!

Ẹni iná ọ̀rẹ́ bá jó rí, bó bá ní’hun nínú kò ní lè rò
ọ̀rẹ́ gidi ń bẹ bíi ká f’ẹ́ni dé’nú
ọ̀rẹ́ ló ṣe’ni l’ọ́ṣẹ́ tó ku s’ára bí iṣu
Ìrètí nínú ènìyàn, irọ́ funfun gbáláhú!
ọ̀rẹ́ kan tí mo ní
Elédùmarè, Alágbára, ìbà Rẹ o Baba, Atóbijù!

Ìbà! ìbà!!

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button

Originally posted 2015-10-02 19:50:39. Republished by Blog Post Promoter

“Awọ kò ká Ojú ìlù, Ọmọ Onílù ni òhun fẹ́ má a sun Awọ jẹ – Ojúkòkòrò àwọn Òṣèlú Nigeria”: “Not enough Leather for drum making, the drummer boy is craving for leather meat delicacy: Greedy Nigerian Politicians”

Nigbati àwọn Òṣèlú gba Ìjọba ni igbà keji lọ́wọ́ Ìjọba Ológun, inú ará ilú dùn nitori wọn rò wi pé Ológun kò kọ iṣẹ́ Òṣèlú.  Ilú rò wi pé Ìjọba Alágbádá yio ni àánú ilú ju Ìjọba Ológun lọ.  Ó ṣe ni laanu pé fún ọdún mẹ́rìndínlógún ti Òṣèlú ti gba Ìjọba, wọn kò fi hàn pé wọn ni àánú ará ilú rárá.  Dipò ki wọn ronú bi nkan yio ti rọrùn fún ilú nipa ipèsè ohun amáyédẹrùn bi iná mọ̀nàmọ́ná, ilé-iwé, ilé-ìwòsàn, ojú ọ̀nà ti ó dára, òfin lati jẹ ki ilú tòrò, ṣe ni wọn bẹ̀rẹ̀ si ji owó ilú.  Bi ori bá fọ́ Òṣèlú, wọn á lọ si Òkè-Òkun nibiti wọn kó owó ti ó yẹ ki wọn fi tú ilé-ìwòsàn ṣe si.  Àwọn Òṣèlú Òkè-Òkun nfi owó Nigeria tọ́jú ará ilú wọn nitori eyi, gbogbo ọ̀dọ́ Nigeria ti kò ni iṣẹ́ fẹ́ lọ si Òkè-Òkun ni ọ̀nà kọnà.

Ọmọ Onilù - The Drummer. Courtesy: theyorubablog

Ọmọ Onilù – The Drummer. Courtesy: theyorubablog

Òwe Yorùbá ti ó sọ wi pé “Awọ kò ká Ojú ìlù, Ọmọ Onilù ni òhún fẹ́ má a sun Awọ jẹ” bá ìròyìn ti ó jáde ni lọ́wọ́-lọ́wọ́, bi àwọn Òṣèlú ti bá owó ọrọ̀ ajé Nigeria jẹ nipa bi wọn ti ṣe pin owó ohun ijà fún Ológun lati ra ibò.  ‘Epo Rọ̀bì’ ni ‘Awọ’ nitori ó lé ni idá ọgọrin ti owó epo rọ̀bì kó ni owó ọrọ̀ ajé ti ilú tà si Òkè-Òkun.  Fún bi ọdún mẹ̃dógún ninú ọdún merindinlogun ti Èrò Ẹgbẹ́ Òṣèlú (ti Alágboòrùn) fi ṣe Ìjọba ki ó tó bọ lọ́wọ́ wọn ni ọdún tó kọjá, owó epo rọ̀bì lọ si òkè rẹpẹtẹ, ọrọ̀ ajé yoku pa owó wọlé.  Dipò ki wọn lo owó ti ó wọlé lati tú ilú ṣe, wọn bẹ̀rẹ̀ si pin owó lati fi ra owó Òkè-Òkun lati kó jade lọ ra ilé nlá si àwọn ilú wọnyi lati sá fún ilú ti wọn bàjẹ́ ni gbogbo ọ̀nà.

Owó epo rọ̀bì fọ́, awọ kò wá ká ojú ilú mọ́.  Oníṣẹ́ Ìjoba kò ri owó-oṣ̀ù gbà déédé, àwọn ti ó fi ẹhin ti ni iṣẹ́ Ìjọba kò ri owó ifẹhinti wọn gba, owó ilú bàjẹ́, bẹni àwọn Òṣèlú bú owó oṣ́u rẹpẹtẹ fún ara wọn.  Eyi ti ó burú jù ni owó rẹpẹtẹ miran ti wọn bù lati ra ọkọ ti ìbọn ò lè wọ, olówó nla lati Òkè-Òkun fún Ọgọrun-le-mẹsan Aṣòfin-Àgbà.   Olóri Aṣòfin-Àgbà fẹ ra ọkọ̀ mẹsan fún ara rẹ nikan.

Àsìkò tó ki àwọn èrò ji lati bá àwọn olè wọnyi wi, nitori àwọn Òṣèlú Òkè-Òkun nibiti wọn nkó owó ilú lọ, kò fi owó ilú wọn tọ́jú ara wọn, wọn nwọ ọkọ̀ pẹ̀lú àwọn ará ilú, àyè kò si fún wọn lati ja ilú ni olè bi ti àwọn Òṣèlú Nigeria.

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button

Originally posted 2016-02-19 10:12:16. Republished by Blog Post Promoter

“Ilú-Oyinbo dára, ọ̀rẹ́ mi òtútù pọ̀” – “Europe is beautiful, but my friend it is too cold.

Thumbnail

Emperor Dele Ojo & His Star Brothers Band – Ilu Oyinbo Dara

Gẹgẹbi, àgbà ninu olórin Yorùbá “Délé Òjó” ti kọ ni ọpọlọpọ ọdún sẹhin pe “Ilú Oyinbo dára, ọrẹ mi òtútù pọ̀, à ti gbọmọ lọwọ èkùrọ́ o ki ma i ṣojú bọ̀rọ̀”.  Àsikò òtútù ni àlejò ma ńṣe iranti ilé.  Òtútù ò dára fún arúgbó, a fi ti onilé nã bá lówó lati san owó iná ti o gun òkè nitori àti tan ẹ̀rọ-amúlé gbónọ́.

 

Yinyin – Snow. Courtesy: @theyorubablog

Ìmọ̀ràn fún àwọn ti ó gbé ìyá wọn wá si ìlú-oyinbo, ni ki wọn gbiyànjú lati ṣe ètò fún àwọn ìyá-àgbà lati lọ si ilé ni asiko òtútù lati fara mọ́ àwọn enia wọn. Òtútù o dára fún eegun àgbà.

ENGLISH TRANSLATION

According to an elder Yoruba musician’s “Dele Ojo” song many years ago, “Europe is very beautiful but my friend it is too cold, cracking palm kernel is no mean task”.  Visitors or migrants often remember home during winter.  Cold is not good for the elderly, except if the home owner can afford the high bill spent in heating the home at this period. Continue reading

Share Button

Originally posted 2016-01-22 06:43:52. Republished by Blog Post Promoter

Ìṣe Ilé ló mbá ni dode – Trudy Alli-Balogun ja Ilé-Iṣẹ́ rẹ lólè – The character cultivated at home often reflect in the public – Trudy Alli-Balogun a Council Officer jailed for £2.4 million housing fraud

Ìbá ṣe pọ̀ laarin Yorùbá àti Ìlú-Ọba ti lé ni igba ọdún nitori òwò Òkè-òkun, pàtàki òwò ẹrú àti fún ẹ̀kọ́ ni ilé iwé giga.  Nitori eyi, àṣà àti èdè Yorùbá kò ṣe fi ọwọ́ rọ sẹhin.

fraud.jpg

Trudy Alli-Balogun jailed for 5 years over £2.4 million housing fraud

Ni Ilú-Ọba, ẹ̀tọ́ ará ilú ni ki Ìjọba pèsè ohun amáyédẹrùn, pàtàki ibùgbé fún ọmọ ilú, ilé-ìwòsàn ọ̀fẹ́ fún ọmọ àti ará ilú.  Àwọn ẹ̀tọ́ wọnyi kò tọ́ si àlejò, ẹni ti ó fi èrú wọ ilú ti kò ni àṣẹ igbelu, tàbi ẹni tó ni iwé lati ṣe iṣẹ ṣùgbọ́n ko ti i di ará ilú.  Ẹni ti ó ni iwé-igbelu lati ṣe iṣẹ́ ti ko ti di ará ilú kò ni ẹ̀tọ́ si ilé Ìjọba, ṣùgbọ́n wọn ni ẹ̀tọ́ si ilé-ìwòsàn ọ̀fẹ́. Iwé ìròyìn irọlẹ, gbe jade bi Trudy Alli-Balogun, ti lo ipò rẹ ni ilé iṣẹ́ ti ó nṣe ipèsè ibùgbé fún ọmọ ilú, lati gba àbẹ̀tẹ́lẹ̀ lọ́wọ́ àwọn Yorùbá ti kò ni ẹ̀tọ́ si irú ilé bẹ́ ẹ̀.  Wọn ṣe ìdájọ́ ẹ̀wọ̀n ọdún marun fún.

Ìròyìn ti ó gbòde ni inu iwé ìròyìn  àti lori ayélujára fi han bi àwọn Olóri Òṣèlú, Aṣòfin àgbà nla àti kékeré, òṣiṣẹ́ Ìjọba àgbà àti àwọn ti ó wà ni ipó giga ni Nigeria ti lo ipò wọn lati fi ja ilu lólè.  Àyipadà ni Ìjọba pẹ̀lú pe Olóri Òṣèlú Muhammadu Buhari/Yẹmi Osinbajo ti ó gbógun ti iwà ibàjẹ́, ló jẹ ki àṣiri iṣẹ́ ibi wọnyi jade si ará ilú bi àwọn ti ó  wà ni ipò giga ti nlo ipò lati fi hu iwà ibàjẹ́ nitori àti kó ọrọ̀ jọ ni ọ̀nà ẹ̀bùrú.

Yorùbá sọ wi pé “Ìṣe ilé ló mbá ni dode”.  Ni àtijọ́, àṣà Yorùbá ni lati wá idi bi enia ti kó ọrọ̀ jọ, ṣùgbọ́n ni ayé òde oni, olówó ni wọ́n mbọ, bi ó bá ti ẹ jalè tàbi ti ẹ̀wọ̀n de nitori iṣẹ́ ibi.  Àyipadà burúkú yi ni obìnirin Trudy Alli-Balogun gbé dé ẹnu iṣẹ́ lati ja ilé iṣẹ́ rẹ ni olè ọ̀kẹ́ aimoye, ti ó si na owó bẹ́ ẹ̀ ni ìná àpà lai ronú orúkọ burúkú ti ó rà fún Yorùbá àti gbogbo orilẹ̀ èdè Nigeria ni Ilú-Ọba àti pé irú iwà ibàjẹ́ yi ló ba ohun amáyédẹrùn jẹ ni Nigeria.  Iwà ibàjẹ́ kò ni orúkọ meji, ẹni ba jalè ba ọmọ jẹ́.

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button

Originally posted 2016-05-06 23:39:56. Republished by Blog Post Promoter

“Ìṣòro ti Agbalésanwó n ri ni Ilú Nlá lati ri Ibùgbé”– “Prospective Tenants’ troubles of finding Accommodation in the Big Cities”

Abúlé – A Village.  Courtesy: @theyorubablog

Abúlé – A Village. Courtesy: @theyorubablog

Ni ayé àtijọ́, kò si ohun ti ó njẹ́ Agbalésanwó nitori kò si ẹni ti kò ni ẹbi ti wọn lè bá gbé ni ọ̀fẹ́.  Kò wọ́pọ̀ ki èniyàn kúrò ni ilé lati lọ gbé ilú miran.  Iṣẹ́ meji ti ó wọ́pò ni ayé àtijọ́ ni iṣẹ́ àgbẹ̀ àti òwò nipa ti ta irè oko ni ọjọ́ Ọjà Oko lati Abúlé kan si ekeji.  Kò si ohun irinna bi ayé òde òni, nitorina ẹsẹ̀ ni wọn fi nlọ lati ilú kan si ekeji.  Yorùbá fẹ́ràn àlejò, nitori eyi, bi Oniṣòwò bá lọ si Ọjà Oko ni ilú miran, ti kò lè délé ni ọjọ́ ti ó gbéra, yio ri ilé sùn ni abúlé ti ó bá dé ti ilẹ̀ fi ṣú lai sanwó.  Olóko ni o ma npèsè ibùgbé fún Alágbàṣe ti wọn bá gbà fún iṣẹ́ oko, nitori eyi, kò si pé àlejò gba ilé lati sanwó.

Ìsọ̀ Ọjà oko – Village Market Stall

Ìsọ̀ Ọjà oko – Village Market Stall. Courtesy: @theyorubablog

Ni igbà ti ó yá, èrò bẹ̀rẹ̀ si kúrò lati ilú kan si ekeji, pàtàki nitori ọ̀gbẹlẹ̀, iyàn, ogun tàbi ẹni ti wọn lé kúrò ni ilú nitori iwà burúkú.  Eleyi fã ki ilú kan fẹ̀ ju òmíràn lọ, pàtàki ni ilú ti ó bá sún mọ́ odò nla bi ti ilù Èkó nitori iṣẹ́ ma npọ̀.

Ni ayé òde òni, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọ̀dọ́ má a nkúrò ni ilé lati wá iṣẹ́ lọ si ilú miran.  Ó rọrùn fún ẹni ti ó kàwé àti oníṣẹ́ ọwọ́ lati ri iṣẹ́ nitori oriṣiriṣi iṣẹ́ pọ ni ilú nlá, ju ilú kékeré lọ.  Eleyi jẹ́ ki ilú nlá bẹ̀rẹ̀ si fẹ si. Gẹ́gẹ́ bi òwe Yorùbá “Ọ̀kọ́lé kò lè mu ràjò”, bẹni kò si bi ẹni ti ó kúrò ni ilé ti lè gbé ilé dáni lọ si ilú nlá. Àlejò bẹ̀rẹ̀ si pọ̀ si ni ilú nlá ṣùgbọ́n ilé gbigbé kò kári.

Àṣà ti ó wọ́pọ̀ ni ki Onilé gba owó ọdún kan tàbi meji.  Elòmìràn ngba ọdún mẹta fún owó à san silẹ̀.  Ilé wá di ohun à mu ṣowó.  Oriṣiriṣi àwọn oniṣẹ́ “Abániwálé” wá pọ̀ si.  ọ̀pọ̀ Onilé àti Abániwále bẹ̀rẹ̀ si lu jìbìtì nipa gbi gba owó lọ́wọ́ ọ̀pọ̀lọpọ̀ Agbalésanwó lóri ilé kan ṣoṣo, òmíràn ngba owó lóri ilé ti ki ṣe ti wọn. Yorùbá ni “Alágbàtà tó nsọ ọjà di ọ̀wọn”, bi ilé bá ti wọn tó ni owó ti Abániwále má a ri gbà ti pọ̀ tó.  Eyi jẹ́ ki wọn sọ ilé di ọ̀wọ́n, nitori owó ti wọn má a ri gbà lọ́wọ́ Onilé àti Agbalésanwó lai ro inira Agbalésanwó.

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button

Originally posted 2015-09-04 07:30:37. Republished by Blog Post Promoter

Bẹni, Bẹ́ẹ̀kọ́ Ìbò Ọ̀rọ̀ Ìlú ni Ìlú-Ọba: Ẹ̀kọ́ fún Orilẹ̀-èdè Nigeria – ‘Yes or No’ The United Kingdom Referendum: Lessons for the Nigerian Nation

Ì̀bò Ọ̀rọ̀ Ìlu ni Ìlú-Ọba' UK Referendum

Ì̀bò Ọ̀rọ̀ Ìlu ni Ìlú-Ọba’ UK Referendum

Ni Ìlú-Ọba, lẹhin ọdún mẹtalelogoji, èrò jade lati di ìbò bẹni-bẹ́ẹ̀kọ́ lori àjọṣepọ̀ pẹ̀lú ẹgbẹ́ Ìlú-Oyinbo méjidinlọ́gbọ̀n ni Ọjọ́bọ̀, oṣu Kẹfa, ọdún Egbàálémẹẹdógún.   Idibò na a lọ wẹ́rẹ́ lai si ìjà, kò gbà ju ìṣéjú kan si meji lọ lati wọlé dibò ti ó  bẹ̀rẹ̀ ni agogo meje àárọ̀ titi di aago mẹwa alẹ́.  Lẹhin idibò, ni òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ keji idibò, ni ọjọ́ Ẹti, ọjọ́ kẹrinlélógún, oṣù kẹfa, èsi ibò jade pé ibò bẹ́ẹ̀kọ́ ju ibò bẹni lọ, eyi ti ó túmọ̀ si wi pé, ará ilú ti ó fẹ́ ki wọn ‘kúrò’ ni ẹgbẹ́ Ilú-Oyinbo pọ̀ ju àwọn ti wọn ó fẹ́ ki wọn ‘dúró‘ ninú ẹgbẹ́.

Bi èsì ibò ti jade, Olóri Òṣèlú Ilú-Ọba, David Cameron, jade lati bá ará ilú sọ̀rọ̀.  Ninú ọ̀rọ̀ rẹ, ó ni nitori ohun polongo ki wọn dúró ninú ẹgbẹ́ Ilú-Oyinbo ṣùgbọ́n àwọn aráilú ti sọ̀rọ̀ wi pé ki wọn kúrò, nitori eyi ohun yio gbé Ijọba silẹ̀.

Ẹ̀kọ́ fún Ìjọba tiwa ntiwa ni orilẹ̀ èdè Nigeria ni wi pé iwá ibàjẹ́ ti àwọn Òṣèlú nhu ni Àbùjá lai fi eti si ará ilú pé àwọn ẹ̀yà mẹ́yà orilẹ̀ èdè Nigeria fẹ́ dá Ìjọba wọn ṣe ju ki Òṣèlú joko si Àbùjá lati maa na owó gbogbo ará ilú.  Ó yẹ ki wọn ronú bi wọn yio ti ṣe Ìjọba ti yio mu irọ̀rùn ba gbogbo ipinlẹ Nigeria.  Ki wọn fi eti si ohun ti ará ilú lati Guusu dé Àriwá sọ, pé ki wọn joko sọ̀rọ̀ bi wọn yio ti ma bára gbé.  Igbe àwọn Igbo ti pọ si lẹhin ti wọn jagun abẹ́lé, àwọn ẹya miran bi Yorùbá nkun ni abẹ́lẹ̀ pé àwọn ma fẹ dá dúró ki wọn san iṣákọ́lẹ̀ fún Ìjọba àpapọ̀.

Ó yẹ ki Òṣèlú Nigeria ṣe àyẹ̀wò òfin ti aṣojú Ilú Ọba – Lugard fi da Guusu àti Àríwá pọ fún irọ̀rùn ìṣàkóso orilẹ̀ èdè Nigeria ni ọgọrunlemeji ọdún sẹhin.  Nigeria gba Òmìnira ni bi ọdún mẹrindinlọgọta sẹhin.  Lẹhin Òmìnira, àwọn Òṣèlú pàtàki ni Ìwọ̀-oòrùn lábẹ́ Olóògbé Olóyè Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ fi ipò Òṣèlú ṣe iṣẹ́ ribiribi lati jẹ́ ki àwọn ará ilú jẹ èrè Òmìnira, ṣùgbọ́n lati igbà ti Ìjọba Ológun ti ó fi ibọn gba Ìjọba ti bẹ̀rẹ̀ si ṣe Òṣèlú ni ilú ti bàjẹ́ si, wọn si rò wi pé àwọn lé fi ipá kó orilẹ̀ èdè pọ.

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button

Originally posted 2016-06-24 13:52:05. Republished by Blog Post Promoter

Ewu ifi Ilé-àpèjẹ dipò Ilé-ìkàwé, MTN fẹ́ gbé Ilé-ìkàwé kúrò ni Ilé-iwé Giga ti Àkokà – The danger of replacing the Library with Event Place, as Donor MTN announced intent to relocate Digital Library from UNILAG

 Ilé-ìkàwé MTN - MTN to withdraw multi-million digital library donated to UNILAG

Ilé-ìkàwé MTN – MTN to withdraw multi-million digital library donated to UNILAG

Ilé-ìkàwé gẹ́gẹ́ bi orúkọ yi ti jẹ ni èdè Yorùbá, jẹ ibi ti wọn kó oriṣiriṣi iwé si, fún ọmọ ilé-iwé àti èrò lati wọlé yá iwé fún ki kà.  Ilẹ̀ Aláwọ̀dúdú ni Ilé-ìkàwé ti bẹ̀rẹ̀ ni Alexandria, Egypt.  Ni ayé òde òni, ki ṣe iwé nikan ni wọn nkó si Ilé-ìkàwé, wọn a tún pèsè ẹ̀rọ ayélujára fún ẹni ti ó bá fẹ́ ka iwé lóri ayélujára àti lati wá idi ohun ti ó nlọ ni àgbáyé.

Ilé́-iwé kò pé lai si Ilé-ìkàwé.  Ki ṣe ilé-iwé nikan ló ni Ilé-ìkàwé, nitori àdúgbò, agbègbè àti ilú na a ma nni Ilé-ìkàwé fún ọmọ ilé-iwé àti èrò ti ó ni ìfẹ́ lati ni ìmọ̀.  Lati igbà ti Ìjọba-àpapọ̀ ti gba gbogbo ilé-iwé lọ́wọ́ àwọn Olùdásílẹ̀, ni ilé-iwé ti bàjẹ́ pàtàki àwọn ilé-iwé ti Ìjọba gba.

Yorùbá fẹ́ràn ẹni ti ó bá kàwé, ṣùgbọ́n ni ayé òde òni, ìfẹ́ owó àti ìgbádùn ti dipò ìfẹ́ ẹ̀kọ́, nitori eyi Ilé-àpèjẹ pọ ni ilú ju Ilé-ìkàwé lọ.  Eyi ti ó burú jù ni pé, kò si Ilé-ìkàwé tuntun, eyi ti ó wà kò ri àtúnṣe.  Ìròyìn gbe jade pé, Ilé-iṣẹ ẹ̀rọ ìbánisọ̀rọ̀ ti ṣe tán lati gbé Ilé-ìkàwé ti wọn kọ́ ni ọdún mẹwa sẹhin fún lilò ni ilé-iwé giga ti ó wà ni Àkokà, ilú Èkó, kúrò nitori wọn ti i pa lati ọdún marun lai lò.  Eleyi yẹ kó ti ará ilú àti Òṣèlú lójú nitori, Ilé-ìkàwé ti wọn ti kọ́ ni ọgọrun ọdún sẹhin tàbi jù bẹ ẹ lọ ṣi wà ni Òkè-Òkun.

Ilú kò lè ni ìlọsíwájú lai si ẹ̀kọ́ àti ìmọ̀ nitori “Ìgbádùn tàbi Eré ṣi ṣe lai ṣi iṣẹ́, ló nfa Ìṣẹ́”.

ENGLISH TRANSLATION

Library as the name literarily suggested in Yoruba, is place where various kinds of books are kept, for Students and the public, where they can borrow books to read.  The oldest Library started in Alexandria, Egypt in 300 BC.  Nowadays, not only books are kept in the Library, Computers with internet are provided for those who want to read or carry out research on happenings around the world. Continue reading

Share Button

Originally posted 2015-06-05 10:00:23. Republished by Blog Post Promoter