Tag Archives: UNILAG

“Bàbá Ìtàn Ìkọ̀lé-Èkìtì, Olóògbé Ọj̀ọ̀gbọ́n-Àgbáyé Adé Àjàyí relé” – “The Father of History of Ikole-Ekiti, Late Professor Emeritus Ade Ajayi has gone home”

Babá re lé ò,
Ilé ló lọ́ tarà-rà
Bàbá re lé ò,
Ilé ló lọ́ tarà-rà
Ilé ò, ilé, Ilé ò, ilé,
Babá re lé ò,
Ilé ló lọ́ tarà-rà

Ni Àṣà Yorùbá, ọmọdé ló nkú, àgbà ki kú, àgbà ma nrelé ni.  Ọ̀fọ̀ ni ikú ọmọdé jẹ́, ijó àti ilú ni wọn fi nṣe ìsìnku àgbà lati sín dé ilé ikẹhin.  Ìròyìn ikú Ọj̀ọ̀gbọ́n-Àgbáyé Adé Àjàyí kàn lẹhin ikú rẹ ni ọjọ́ kẹsan, oṣù kẹjọ,ọdún Ẹgbã-le-mẹrinla.  A bi ni ilú Ìkọ̀lé-Èkìtì ni ọdún marun-le-lọgọrin sẹhin.  Ọ̀pọ̀lọpọ̀ Ọ̀jọ̀gbọ́n, ọmọdé àti àgbà ilú lati onírúurú iṣẹ́àti àwọn èniyàn pàtàki ni ilé-lóko péjọ ni ọjọ kọkàn-din-logun, oṣù kẹsan,ọdún Ẹgbã-le-mẹrinla lati ṣe ìsìnku rẹ.

http://www.ngrguardiannews.com/news/national-news/179784-eulogies-as-eminent-scholar-ade-ajayi-is-buried

Olóògbé Ọj̀ọ̀gbọ́n-Àgbáyé Adé Àjàyí - Late Professor Emeritus Ade Ajayi

Olóògbé Ọj̀ọ̀gbọ́n-Àgbáyé Adé Àjàyí – Late Professor Emeritus Ade Ajayi

Ọ̀rọ̀ Yorùbá sọ pé “Ẹni ti kò bá mọ ìtàn ara rẹ, yio dahun si orúkọ tí kò jẹ́”.  Ki awọn bi Olóògbé tó bẹ̀rẹ̀ si kọ Ìtàn Yorùbá àti ilẹ́ Aláwọ̀-dúdú silẹ̀, àwọn Aláwọ̀-funfun kò rò pé Aláwọ̀-dúdú ni Ìtàn nitori wọn kò kọ silẹ̀, wọn nsọ Ìtàn lati ẹnu-dé-ẹnu ni.  Nitori eyi, ohun ti ó wu Aláwọ̀-funfun ni wọn nkọ.  Olóògbé Ọj̀ọ̀gbọ́n-Àgbáyé Adé Àjàyí, kọ́ ẹ̀kọ́, ó si gboyè rẹpẹtẹ lori Ìtàn, pàtàki lati jẹ́ ki Yorùbá mọ ìtàn ara wọn.  Ó lo imọ̀ yi lati kọ ọ̀pọ̀lọpọ̀ iwé itan, ikan lára iwé wọnyi ni “Ìtàn àti Ogun jijà Yorùbá”.  Ó tún kọ nipa Ìgbési-ayé “Olóògbé Olóri àwọn Alufaa Àjàyí Crowther” àti “Onidajọ Káyọ̀dé Ẹ̀ṣọ́”.

Yorùbá pa òwe pé “Àgbà ki wà lọ́jà, ki ori ọmọ titun wọ”, Olóògbé Ọj̀ọ̀gbọ́n-Àgbáyé Adé Àjàyí ni Igbá-keji Ilé-ẹ̀kọ́ Giga, Èkó kẹta.  Nitori ìfẹ́ ti ó ni si ìdàgbà sókè Ilé-ẹ̀kọ́ Giga, ìtàn àti ìpamọ́ ohun-ìtàn, ó kọ iwé si Olóri Òṣèlú Nigeria (Goodluck Ebele Jonathan), nigbà Ìporúkọdà lójiji lati Ilé-ẹ̀kọ́ Giga Èkó si orúkọ Olóògbé MKO Abiọ́lá – ti gbogbo ilú dibò fún lati ṣe Olóri Òṣèlú, ṣùgbọ́n àwọn Ìjọba Ológun kò jẹ́ kó dé ipó yi.  Olóri Òṣèlú Nigeria yi ọkàn padà lati ma yi orúkọ Ilé-ẹ̀kọ Giga yi padà lojiji nitori ọ̀wọ̀ ti ó ni fún Olóògbé. Continue reading

Share Button

Originally posted 2014-09-26 17:56:15. Republished by Blog Post Promoter

Ewu ifi Ilé-àpèjẹ dipò Ilé-ìkàwé, MTN fẹ́ gbé Ilé-ìkàwé kúrò ni Ilé-iwé Giga ti Àkokà – The danger of replacing the Library with Event Place, as Donor MTN announced intent to relocate Digital Library from UNILAG

 Ilé-ìkàwé MTN - MTN to withdraw multi-million digital library donated to UNILAG

Ilé-ìkàwé MTN – MTN to withdraw multi-million digital library donated to UNILAG

Ilé-ìkàwé gẹ́gẹ́ bi orúkọ yi ti jẹ ni èdè Yorùbá, jẹ ibi ti wọn kó oriṣiriṣi iwé si, fún ọmọ ilé-iwé àti èrò lati wọlé yá iwé fún ki kà.  Ilẹ̀ Aláwọ̀dúdú ni Ilé-ìkàwé ti bẹ̀rẹ̀ ni Alexandria, Egypt.  Ni ayé òde òni, ki ṣe iwé nikan ni wọn nkó si Ilé-ìkàwé, wọn a tún pèsè ẹ̀rọ ayélujára fún ẹni ti ó bá fẹ́ ka iwé lóri ayélujára àti lati wá idi ohun ti ó nlọ ni àgbáyé.

Ilé́-iwé kò pé lai si Ilé-ìkàwé.  Ki ṣe ilé-iwé nikan ló ni Ilé-ìkàwé, nitori àdúgbò, agbègbè àti ilú na a ma nni Ilé-ìkàwé fún ọmọ ilé-iwé àti èrò ti ó ni ìfẹ́ lati ni ìmọ̀.  Lati igbà ti Ìjọba-àpapọ̀ ti gba gbogbo ilé-iwé lọ́wọ́ àwọn Olùdásílẹ̀, ni ilé-iwé ti bàjẹ́ pàtàki àwọn ilé-iwé ti Ìjọba gba.

Yorùbá fẹ́ràn ẹni ti ó bá kàwé, ṣùgbọ́n ni ayé òde òni, ìfẹ́ owó àti ìgbádùn ti dipò ìfẹ́ ẹ̀kọ́, nitori eyi Ilé-àpèjẹ pọ ni ilú ju Ilé-ìkàwé lọ.  Eyi ti ó burú jù ni pé, kò si Ilé-ìkàwé tuntun, eyi ti ó wà kò ri àtúnṣe.  Ìròyìn gbe jade pé, Ilé-iṣẹ ẹ̀rọ ìbánisọ̀rọ̀ ti ṣe tán lati gbé Ilé-ìkàwé ti wọn kọ́ ni ọdún mẹwa sẹhin fún lilò ni ilé-iwé giga ti ó wà ni Àkokà, ilú Èkó, kúrò nitori wọn ti i pa lati ọdún marun lai lò.  Eleyi yẹ kó ti ará ilú àti Òṣèlú lójú nitori, Ilé-ìkàwé ti wọn ti kọ́ ni ọgọrun ọdún sẹhin tàbi jù bẹ ẹ lọ ṣi wà ni Òkè-Òkun.

Ilú kò lè ni ìlọsíwájú lai si ẹ̀kọ́ àti ìmọ̀ nitori “Ìgbádùn tàbi Eré ṣi ṣe lai ṣi iṣẹ́, ló nfa Ìṣẹ́”.

ENGLISH TRANSLATION

Library as the name literarily suggested in Yoruba, is place where various kinds of books are kept, for Students and the public, where they can borrow books to read.  The oldest Library started in Alexandria, Egypt in 300 BC.  Nowadays, not only books are kept in the Library, Computers with internet are provided for those who want to read or carry out research on happenings around the world. Continue reading

Share Button

Originally posted 2015-06-05 10:00:23. Republished by Blog Post Promoter

A kì dàgbà jẹ Òjó: Natural birth names not apt at old age — ÌDÁRÚKỌ PADÀ UNILAG – THE UNILAG NAME CHANGE

Univesity of Lagos Senate

UNILAG Senate Building – photo from http://www.unilag.edu.ng/

“A kì dàgbà jẹ Òjó”: “Natural birth names not appropriate at old age”

Òjó, Dàda, Àìná, Táíwò, Kẹhinde ati bebe lo je orúkọ amu tọrun wa.  Pípa orúkọ Ilé-ìwé gíga ni Akoka, ilu Eko da lẹhin aadọta ọdún dàbí ìgbà ti a sọ arúgbó lorukọ àmú tọrun wa.  Apẹrẹ: ẹni ti ki ṣe ibeji ko le pa orúkọ da si orúkọ àmú tọrun wa.

A dupẹ lọwọ Olórí Ìlú Goodluck Jonathan to gbọ igbe awọn ènìyàn lati da orúkọ Ilé-ìwé Gíga ti o wa ni Akoko ti Ilu Eko pada gẹgẹbi Olukọagba Jerry Gana, ti kọ si ìwé ìròyìn ni ọjọ Ẹti, oṣù keji ẹgbaa le mẹtala.

ENGLISH TRANSLATION

Òjó, Dàda, Àìná, Táíwò, Kẹhinde etc, all these names in Yoruba are given at birth as a result of natural circumstances observed at birth.  Continue reading

Share Button