Tag Archives: Respect

Bi ọmọ ò jọ ṣòkòtò á jọ kíjìpá: Ibáṣe pọ Idilé Yorùbá – If a child does not take after the father, he/she should take after the mother – Yoruba Family Relationship

Bàbá, iyá àti ọmọ ni wọn mọ si Idilé ni Òkè-òkun ṣùgbọ́n ni ilẹ̀ Yorùbá kò ri bẹ́ ẹ̀, nitori ẹbi Eg bàbá, ẹ̀gbọ́n àti àbúrò ẹni, ọmọ, ọkọ àti aya wọn ni a mọ̀ si Idilé.  Yorùbá fẹ́ràn lati má a bọ̀wọ̀ fún àgbà nitori eyi, ẹni ti ó bá ju Bàbá àti Ìyá ẹni lọ Bàbá tàbi Ìyá la n pè é, wọn ki pe àgbà ni orúko nitori eyi, wọn lè fi orúkọ ọmọ pe àgbà tàbi ki wọn lo orúkọ apejuwe (bi Bàbá Èkó, Iyá Ìbàdàn).  Ẹ ṣe à yẹ̀ wò àlàyé àti pi pè ibáṣepọ̀ idilé ni ojú iwé yi.

The Western family is made up of, father, mother and their children but this is not so, as Yoruba family on the other hand is made up of extended family that includes; father, mother, children, half/full brothers/sisters, step children, cousins, aunties, uncles, maternal and paternal grandparents.  Yoruba people love respecting the elders, as a result, uncles and aunties that are older than one’s parents are called ‘Father’ or ‘Mother’ and elders are not called by their names as they are either called by their children’s name or by description (example Lagos Father, Ibadan Mother)  Check the explanation and prononciation below.

Share Button

Originally posted 2015-10-27 22:57:10. Republished by Blog Post Promoter

“Orin ẹ̀kọ́ lati bọ̀wọ̀ fún òbí ni ilé-ìwé alakọbẹrẹ”: Primary School song to teach respect for parents

Orin yi ni Olùkọ́ ma fi ńkọ́ àwọn ọmọ ilé-ìwé alakọbẹrẹ nigbà “ilé-ìwé ọ̀fẹ́” ti àwọn Òṣèlú ilẹ̀ Yorùbá ti Olóyè Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ̀ ṣe olórí rẹ.  Ni ayé ìgbà wọnyi, ọ̀pọ̀lọpọ̀ òbí a ma fi ebi panú, ṣiṣẹ́ kárakára tàbí ta ohun ìní lati pèsè fún àwọn ọmọ àti lati rán ọmọ lọ sí ilé-ìwé gíga.  O yẹ ki ọmọ bọ̀wọ̀ fún irú àwọn òbí wọnyi.

MP3 Below

Download: Omo to moya iya loju – Respect for parents

Ọ́mọ tó mọ̀ yà rẹ lóju ò                                                

Oṣí yo tá mọ náà pàa                                   

Ọ́mọ tó mọ̀ bà rẹ lóju o                               

Oṣí yo tá mọ náà pàa                                   

Iyà rẹ̀ jiyà pọ̀ lorí rẹ                              

Bàbà rẹ̀ jiya pọ̀ lorí rẹ                          

Ọ́mọ tó mọ̀ yà rẹ lóju ò                

Oṣí yo tá mọ náà pàa

Ọ́mọ tó mọ̀ bà rẹ lóju o

Oṣí yo tá mọ náà pàa

ENGLISH TRANSLATION

During the “Free Education Programme in the Western State of Nigeria” that was created by the Politicians led by Chief Obafemi Awolowo, Primary School pupils are thought the song below to teach respect for parents.  At that period, many parents denied themselves of food, worked hard or even sell their properties in order to provide for their children and to educate them in the Higher Institutions.  It is only apt for such children to respect such parents.

The child that disobey his/her parent

Will suffer poverty in the end

The child that disobey his/her father

Will suffer poverty in the end

Your mother suffered so much for you

Your father suffered so much for you

A child that disobey his/her parent

Will suffer poverty in the end

A child that disobey his/her father

Will suffer poverty in the end

 

 

Share Button

Originally posted 2013-07-26 20:21:43. Republished by Blog Post Promoter