Tag Archives: Oba Lamidi Adeyemi

Ìròyìn kàn pé Ọ̀túnba Gani Adams ni Aàrẹ Ọ̀na Kakanfo Yorùbá karùndinlógún – Chief Gani Adams has been announced as the Fifteenth Generalissimo of Yorubaland

Ọba Lamidi Adéyẹmi àti Ọ̀túnba Gani Adams – Aláafin Lamidi Adeyemi & Chief Gani Adams

Lẹhin ọdún kọkàndinlógún ikú Olóògbé Olóyè M.K.O Abíọ́lá, Aàrẹ Ọ̀na Kakanfo Yorùbá kẹ̀rinlá, Ọba Lamidi Adéyẹmi yan Ọ̀túnba Gani Adams si ipò Aàrẹ Ọ̀na Kakanfo Yorùbá karùndinlógún.

Ọ̀túnba Gani Adams ni olùdásílẹ̀ Ẹgbẹ́ Ọ̀dọ́ Ọmọ Oòduà, ti wọn dá silẹ̀ ni ọjọ́ karùndinlọ́gbọ̀n, oṣù kẹjọ ọdún kẹtàlélógún sẹhin ni Mushin, lati jà fún gbi gbé ipò Olórí Òṣèlú fún M.K.O Abiola ti ó mókè ni ìbò ti wọn di ni ọjọ́ kejila ọdún kẹrinlélógún sẹhin lai si ìjà tàbi asọ̀ ni gbogbo orílẹ̀ èdè Nigeria.  Kò bojú wẹ̀hin lati ọdún kẹtàlélógún lati má a jà fún Yorùbá lati gba ẹ̀tọ́, iyì àti gbi gbé àṣà Yorùbá ga kakiri àgbáyé.  Fún akitiyan yi, wọn ti fi jẹ oyè mejilelaadọta kakiri, ṣùgbọ́n adé gbogbo oyè yi ni Aare Ona Kakanfo.

Bi àwọn alatako diẹ ti wa ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ àgbàgbà Yorùbá ti fi ọwọ́ si yin yan Ọ̀túnba Gani Adams si ipò Aare Ona Kakanfo karundinlogun.  Lára àwọn enia pàtàki ti ó ki kú ori ire ni, Ọọni Ifẹ̀, Gómìnà Bọ́la Tinubu, Gómìnà Rauf Arẹ́gbẹ́sọlá, àwọn ọ̀gá olórin àti bẹ́ ẹ̀ bẹ́ ẹ̀ lọ.

Olùkọ̀wé Yorùbá lóri Ayélujára kí Ọ̀túnba Gani Adams kú ori ire, oyè á mọ́rí o, ẹ ò ni kú léwe, ẹmi ọlá á gùn lati má a jà fún Yorùbá àti lati gbé àṣà Yorùbá lárugẹ si, ni gbogbo àgbáyé.

ENGLISH TRANSLATION

Nineteen years after the death of Chief M.K.O. Abiola, the fourteenth Generalissimo of Yorubaland, the Alafin of Oyo, Oba Lamidi Adeyemi has nominated Chief Gani Adams as the 15h Generalissimo of Yorubaland.

Chief Gani Adams was the founder of the Odua Youth Movement which was formed on August 25, 1994 at Mushin, Lagos, to fight for the actualisation of June 12, 1993 Presidential election won by Chief M.KO. Abiola in a free and fair election all over Nigeria.  He has not looked back since he came to prominence in 1994 as he continued to fight to uphold the dignity, honour and culture of his people.  His action of defending and promoting Yoruba culture has earned him fifty-two titles but the crown of all the titles is the Aare Ona Kakanfo.

Although there are some oppositions, many prominent Yoruba leaders have endorsed the nomination of Otunba Gani Adams as the fifteen Aare Ona Kakanfo.  Prominent among them are, Ooni of Ife, Governors – Ahmed Bola Tinubu (former Governor of Lagos State), Rauf Aregbesola (Osun State Governor), prominent Musicians etc.

The Yoruba Blog congratulates Chief Gani Adams and pray that he will not die young but live long to continue in the service of defending Yorubaland and promoting her culture all over the world.

Share Button