Tag Archives: Lagos

Bi mo ṣe lo Ìsimi Àjíǹde tó kọjá – How I spent the last Easter Holiday

Ìsimi ọdún Àjíǹde tó kọjá dùn púpọ̀ nitori mo lọ lo ìsimi náà pẹ̀lú ẹ̀gbọ́n Bàbá mi àti ẹbí rẹ ni ilú Èkó.

Èkó jinà si ilú mi nitori a pẹ́ púpọ̀ ninú ọkọ̀ elérò ti àwọn òbí mi fi mi si ni idikọ̀ ni Ìkàrẹ́-Àkókó ni ipinlẹ̀ Ondó.  Lára ilú ti mo ri ni ọ̀nà ni Ọ̀wọ̀, Àkúrẹ́, Ilé-Ifẹ̀ àti Ìbàdàn.  A dúró lati ra àkàrà ni ìyànà Iléṣà.  Ẹ̀gbọ́n Bàbá mi àti ìyàwó rẹ̀ wa pàdé mi ni idikọ̀ ni Ọjọta ni Èkó lati gbémi dé ilé wọn.

Èkó tóbi púpọ̀, ilé gogoro pọ̀, ọkọ̀ oriṣiriṣi náà pọ̀ rẹpẹtẹ ju ti ilú mi lọ.  Ilé ẹ̀gbọ́n Bàbá mi tóbi púpọ̀.  Wọ́n fún èmi nikan ni yàrá.  Yàrá mi dára púpọ̀, ó ni ilé-ìwẹ̀ àti ilé-ìgbẹ́ ti rẹ̀ lọ́tọ̀.

Ojojúmọ́ ni ẹ̀gbọ́n bàbá mi àti ìyàwó rẹ̀ ngbé mi jade lọ si oriṣiriṣi ibi ni Èkó.  Ni ọjọ́ Ẹtì (Jimọ) Olóyin wọ́n gbé mi lọ si ilé-ìjọ́sìn, ẹsin ọjọ náà fa ìrònú nitori wọn ṣe eré bi wọn ṣe kan Jésù mọ́gi, ṣùgbọ́n ni ọjọ́ Aj̀íǹde, èrò ti ó múra dáradára pọ̀ ni ilé-ìjọsìn, ẹ̀sìn dùn gidigidi.  Mo wọ̀ lára aṣọ tuntun ti ìyàwó ẹ̀gbọ́n Bàbá mi rà fún mi fún ọdún Àjíǹde.  Lati ilé-ìjọ́sìn ọmọdé, àwa ọmọdé jó wọ ilé-ìjọ́sìn  àwọn àgbàlagbà.  Wọn fún gbogbo wa ni oúnjẹ (ìrẹsì àti itan adìyẹ ti ó tóbi) lẹhin isin.  Ni ọjọ́ Ajé, ọjọ́ keji Àjíǹde, a lọ si etí òkun lati lọ gba afẹ́fẹ́.  Ẹ̀rù omi nlá náà bà mi lakọkọ, ṣùgbọ́n nitori èrò àti àwọn ọmọdé pọ̀ léti òkun, nkò bẹ̀rù mọ.  A jẹ oriṣiriṣi oúnjẹ, a jó, mo si tún gun ẹsin leti òkun.

Lẹhin ọ̀sẹ̀ meji ti ilé-iwé ti fẹ́ wọlé, ẹ̀gbọ́n Bàbá mi àti ìyàwó rẹ̀ gbé mi padà lọ si idikọ̀ lati padà si ilú mi pẹ̀lú ẹ̀bún oriṣiriṣi lati fún ará ile.  Inú mi bàjẹ́, kò wù mi lati padà, mo ké nitori mo gbádùn Èkó gidigidi.

ENGLISH TRANSLATION

I really had a nice time during the last Easter/Spring holiday because I spent the holiday with my paternal uncle (my father’s older brother) and his family in Lagos. Continue reading

Share Button

Originally posted 2018-06-15 19:28:13. Republished by Blog Post Promoter

“Ikú tó fẹ́ pani, bó bá sini ni fìlà, ọpẹ́ ló yẹ ká dá”: Idibò yan Òṣèlú ọdún Ẹgbãlemẹ̃dógún – “Escaping death by the whisker calls for gratitude”: Election of Twenty-fifteen

Ni igbà ipalẹ̀mọ́ idibò, ẹ̀rù ba ará ilú nitori wọn kò mọ ohun ti ó lè sẹlẹ̀.  Àwọn ti ó ndu ipò jade ni rẹpẹtẹ fún ètò-òṣèlú, eyi ti ó fa ki àwọn jàndùkú bẹ̀rẹ̀ ijà ti ó fa sún-kẹrẹ fà-kẹrẹ ọkọ̀ pàtàki ni ilú Èkó, eleyi fa ibẹ̀rù pé ọjọ́ idibò yio burú.

Ẹgbẹ́ Onigbalẹ -  APC Logo

Ẹgbẹ́ Onigbalẹ – APC Logo

Yorùbá ni “Ọ̀rọ̀ ki i mi ni ikùn àgbà” ṣùgbọ́n, ọ̀rọ̀ mi ni ikùn Ọba Èkó, Ọba Rilwanu Akiolu nigbati ó ṣe ipàdé pẹ̀lú àwọn àgbà Ìgbò Èkó, pé ti wọn kò bá dibò fún ẹni ti ohun fẹ, wọn yio bá òkun lọ.  Ọ̀rọ̀ Ọba Rilwanu Akiolu bi ará ilé àti oko ninú.  Eleyi tún dá kún ibẹ̀rù pé ija yio bẹ́ ni ọjọ́ idibò, nitori eyi ọpọlọpọ ará ilú ko jade lati dibò.

Gbogbo àgbáyé ló mọ̀ wi pé àwọn Òṣèlú ilẹ̀ Aláwọ̀-dúdú ki i fẹ gbé Ìjọba silẹ.  Ki ṣe pe wọn ni ifẹ́ ilu,́ bi kò ṣe pé, ó gbà wọn láyè lati lo ipò wọn lati ji owó ilú fún ara àti ẹbi wọn.  Gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ Yorùbá pe “Ikú tó fẹ́ pani, bó bá sini ni fìlà, ọpẹ́ ló yẹ ká dá”, ikú tó fẹ́ pa ará ilú ti re kọja nitori ọjọ́ idibò lati yan Gómìnà àti Aṣòfin-ipinlẹ̀ ti lọ lai mú ogun dáni bi ará ilú ti rò.  Ẹ ṣe àyẹ̀wò èsi idibò:

ENGLISH TRANSLATION

Continue reading

Share Button

Originally posted 2015-04-14 19:16:02. Republished by Blog Post Promoter

Olùkọ̀wé Èdè àti Àṣà Yorùbá lóri ayélujára, ki gbogbo ọmọ orílẹ̀ èdè Nigeria kú àjọ̀dún Òmìnira kejìdínlọ́gọ́ta – The Yoruba Blog wishes all Nigerians happy 58th Independence Celebration

Àsíá orílẹ̀ èdè Nigeria – Nigerian Flag.

Fún ọdún mọ́kàndín-lọgọrun lati ìgbà ti Òyìnbó Ìlú-Ọba ti fi ipá gba Èkó titi di ọjọ́ kini oṣù kẹwa, odun Ẹgbẹ̀sánlé-ọkanlelọgọta ti orílẹ̀ èdè Nigeria gba Òmìnira, Òyìnbó Ìlú-Ọba kan èdè Gẹ̀ẹ́sì wọn nípá, wọ́n tún gàba lóri ọrọ adánidá ni orílẹ̀ èdè Nigeria.  Ṣi ṣe ìrántí Òmìnira yẹ kó rán gbobgo ọmọ Nigeria lápapọ̀ létí iṣé takun-takun ti àwọn olóri òṣèlú parapọ̀ ṣe lati tú orílẹ̀ èdè sílẹ̀ lọ́wọ́ àwọn Gẹ̀ẹ́sì, pàtàki bi àwọn olóri òṣèlú Ìlà-oòrùn àti Ìwọ̀-oòrùn ti kó ra pọ̀.  Èyi fi hàn wi pé bi àwọn  òṣèlú ayé òde òní bá fi ìfẹ orílẹ̀ èdè ṣáájú, wọn kò ni fi ẹ̀sìn àti ẹ̀yà bojú lati tú orílẹ̀ èdè ka, èyi ti ó njẹ ki wọn ri àyè jí ìṣúra orílẹ̀ èdè si àpò ara wọn nitori eyi, ó yẹ ki gbogbo ọmọ orílẹ̀ èdè Nigeria ti ó ni ìfẹ́ orílẹ̀ èdè, pẹnupọ̀ lati bá àwọn òṣèlú ti ó nja ilú ló olè wi.

Bi a ṣe nṣe àjọ̀dún Òmìnira kejìdínlọ́gọ́ta yi, ó yẹ ki gbogbo ọmọ orílẹ̀ èdè Nigeria gbé ìfẹ́ lékè ìríra.  Ìfẹ́ ló lè borí li lo ẹ̀yà àti ẹ̀sìn lati pín orílẹ̀ èdè, ti ó tún lè dín ojúkòkòrò àwọn òṣèlú kù.

Lati ọ̀dọ̀ àwọn Olùkọ̀wé Èdè àti Àṣà Yorùbá lóri ayélujára, a ki gbogbo ọmọ orílẹ̀ èdè Nigeria kú àjọ̀dún Òmìnira.

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button

A kì dàgbà jẹ Òjó: Natural birth names not apt at old age — ÌDÁRÚKỌ PADÀ UNILAG – THE UNILAG NAME CHANGE

Univesity of Lagos Senate

UNILAG Senate Building – photo from http://www.unilag.edu.ng/

“A kì dàgbà jẹ Òjó”: “Natural birth names not appropriate at old age”

Òjó, Dàda, Àìná, Táíwò, Kẹhinde ati bebe lo je orúkọ amu tọrun wa.  Pípa orúkọ Ilé-ìwé gíga ni Akoka, ilu Eko da lẹhin aadọta ọdún dàbí ìgbà ti a sọ arúgbó lorukọ àmú tọrun wa.  Apẹrẹ: ẹni ti ki ṣe ibeji ko le pa orúkọ da si orúkọ àmú tọrun wa.

A dupẹ lọwọ Olórí Ìlú Goodluck Jonathan to gbọ igbe awọn ènìyàn lati da orúkọ Ilé-ìwé Gíga ti o wa ni Akoko ti Ilu Eko pada gẹgẹbi Olukọagba Jerry Gana, ti kọ si ìwé ìròyìn ni ọjọ Ẹti, oṣù keji ẹgbaa le mẹtala.

ENGLISH TRANSLATION

Òjó, Dàda, Àìná, Táíwò, Kẹhinde etc, all these names in Yoruba are given at birth as a result of natural circumstances observed at birth.  Continue reading

Share Button