Tag Archives: Ile Ife

Ọba titun, Ọọni Ifẹ̀ Kọkànlélaadọta gba Adé – The new Monarch, Ooni of Ife Received his Crown

Ọọni Ifẹ̀ Kọkànlélaadọta gba Adé – Ooni of Ife Oba Enitan Ogunwusi after receiving the AARE Crown from the Olojudo of Ido land on Monday PHOTOS BY Dare Fasub

Ilé-Ifẹ̀ tàbi Ifẹ̀ jẹ ilú àtijọ́ ti Yorùbá kà si orisun Yorùbá.  Lẹhin ọjọ mọ́kànlélógún ni Ilofi (Ilé Oyè) nigbati gbogbo ètùtù ti ó yẹ ki Ọba ṣe pari, Ọba Adéyẹyè Ẹniitàn, Ògúnwùsi gba Adé  Aàrẹ Oduduwa ni ọjọ́ kẹtàlélógún oṣù kọkànlá ọdún Ẹgbàálemẹ͂dógún ni Òkè Ọra nibiti Bàbá Nlá Yorùbá Oduduwa ti kọ́kọ́ gba adé yi ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún sẹhin.

Ọba Ogunwusi, Ọjaja Keji, di Ọba kọkànlélaadọta Ilé Ifẹ̀, lẹhin ti Ọba Okùnadé Sijúwadé pa ipò dà ni ọjọ́ kejidinlọgbọn, oṣù keje odun Ẹgbàálemẹ͂dógún.

Gẹ́gẹ́ bi àṣà àdáyébá, ẹ͂kan ni ọdún nigba ọdún  Ọlọ́jọ́ ti wọn ma nṣe ni oṣù kẹwa ọdún ni Ọba lè dé Adé Aàrẹ Oduduwa.

Adé á pẹ́ lóri o, bàtà á pẹ́ lẹ́sẹ̀.  Igbà Ọba Adéyẹyè Ẹniitàn, Ògúnwùsi á tu ilú lára.lè dé Adé Àrẹ Oduduwa.

 

 

ENGLISH TRANSLATION

Ile-Ife or Ife is an ancient Yoruba Town that is regarded as the origin of the Yoruba people.  Continue reading

Share Button

Originally posted 2015-11-24 20:04:10. Republished by Blog Post Promoter

Ọọ̀ni Ilé Ifẹ̀, Ọba Okùnadé Alade Sijúwadé, Olúbùṣe Keji Wàjà – The Ooni of Ife, King Okunade Alade Sijuwade has joined his Ancestors

Olóògbé Ọba Sijúwadé Olúbùṣe Keji - Late King Sijuwade, Olubuse II.

Olóògbé Ọba Sijúwadé Olúbùṣe Keji – Late King Sijuwade, Olubuse II.

Ni ọjọ Kejidinlọ́gbọ̀n, oṣù Keje, ọdún Ẹgbãlemẹ͂dógún, iroyin jade ninú àwọn iwé-iroyin àti ori ayélujára pé Ọba Okunade Sijuwade, Olúbùṣe Keji, pa ipò da ni Ilú Ọba.  Àwọn Olóyè Ilé-Ifẹ̀ sẹ́ ọ̀rọ̀ ikú Ọba yi, nitori ni ayé àtijọ́, àwọn àgbà Oyè ló ni àṣẹ lati tú ọ̀fọ̀ pé Ọba wàjà fún ará ilú, nitori gẹ́gẹ́ bi àṣà Yorùbá Ọba ki kú.  Àwọn àgbà Oyè tú ọ̀fọ̀ ni iwá́jú Gómìnà Rauf Arégbẹ́ṣọlá ti ipinlẹ̀ Ọ̀ṣun, ni Ọjọ́rú, ọjọ́ kejila oṣù kẹjọ ọdún Ẹgbãlemẹ͂dógún. Ni ayé òde òni kò si àṣiri mọ, àṣà yi ti yi padà nitori, ni àtijọ́, Ọba ki kú si àjò, bẹni kò si iwé-iroyin àti ẹ̀rọ ayélujára.

Ilé Ifẹ̀ jẹ́ ilú pàtàki ni ilẹ̀ Yorùbá nitori itàn sọ wi pé ibẹ̀ ni orisun Yorùbá pẹ̀lú Bàbá nla Yorùbá “Oduduwa” ti ó tẹ ibẹ̀ dó.   Okùnadé Alade Sijúwadé, Olúbùṣe Keji, gun ori oyè Ọọni Ifẹ̀ nigbati ó pé aadọta ọdún, ó lo ọdún mẹ͂dógóji ni ipò Ọọni Ifẹ̀.  Ohun ni aadọta Ọba Ilé Ifẹ̀.

Ìsìnkú Ọba Sijúwadé bẹ̀rẹ̀ ni ọjọ́ Ẹti, ọjọ́ kẹrinla, oṣù Kẹjọ, ọdún Ẹgbãlemẹ̃dógún.  Lẹhin ìsìnkú, ìséde ọlọ́jọ́ meje yio bẹ̀rẹ̀ ni Ilé-Ifẹ̀ àti agbègbè rẹ lati agogo mẹrin ìrọ̀lẹ́. Ki Èdùmàrè gba olóògbé Ọba Sijúwadé si afẹ́fẹ́ rere.

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button