Tag Archives: EFCC

“Awọ kò ká Ojú ìlù, Ọmọ Onílù ni òhun fẹ́ má a sun Awọ jẹ – Ojúkòkòrò àwọn Òṣèlú Nigeria”: “Not enough Leather for drum making, the drummer boy is craving for leather meat delicacy: Greedy Nigerian Politicians”

Nigbati àwọn Òṣèlú gba Ìjọba ni igbà keji lọ́wọ́ Ìjọba Ológun, inú ará ilú dùn nitori wọn rò wi pé Ológun kò kọ iṣẹ́ Òṣèlú.  Ilú rò wi pé Ìjọba Alágbádá yio ni àánú ilú ju Ìjọba Ológun lọ.  Ó ṣe ni laanu pé fún ọdún mẹ́rìndínlógún ti Òṣèlú ti gba Ìjọba, wọn kò fi hàn pé wọn ni àánú ará ilú rárá.  Dipò ki wọn ronú bi nkan yio ti rọrùn fún ilú nipa ipèsè ohun amáyédẹrùn bi iná mọ̀nàmọ́ná, ilé-iwé, ilé-ìwòsàn, ojú ọ̀nà ti ó dára, òfin lati jẹ ki ilú tòrò, ṣe ni wọn bẹ̀rẹ̀ si ji owó ilú.  Bi ori bá fọ́ Òṣèlú, wọn á lọ si Òkè-Òkun nibiti wọn kó owó ti ó yẹ ki wọn fi tú ilé-ìwòsàn ṣe si.  Àwọn Òṣèlú Òkè-Òkun nfi owó Nigeria tọ́jú ará ilú wọn nitori eyi, gbogbo ọ̀dọ́ Nigeria ti kò ni iṣẹ́ fẹ́ lọ si Òkè-Òkun ni ọ̀nà kọnà.

Ọmọ Onilù - The Drummer. Courtesy: theyorubablog

Ọmọ Onilù – The Drummer. Courtesy: theyorubablog

Òwe Yorùbá ti ó sọ wi pé “Awọ kò ká Ojú ìlù, Ọmọ Onilù ni òhún fẹ́ má a sun Awọ jẹ” bá ìròyìn ti ó jáde ni lọ́wọ́-lọ́wọ́, bi àwọn Òṣèlú ti bá owó ọrọ̀ ajé Nigeria jẹ nipa bi wọn ti ṣe pin owó ohun ijà fún Ológun lati ra ibò.  ‘Epo Rọ̀bì’ ni ‘Awọ’ nitori ó lé ni idá ọgọrin ti owó epo rọ̀bì kó ni owó ọrọ̀ ajé ti ilú tà si Òkè-Òkun.  Fún bi ọdún mẹ̃dógún ninú ọdún merindinlogun ti Èrò Ẹgbẹ́ Òṣèlú (ti Alágboòrùn) fi ṣe Ìjọba ki ó tó bọ lọ́wọ́ wọn ni ọdún tó kọjá, owó epo rọ̀bì lọ si òkè rẹpẹtẹ, ọrọ̀ ajé yoku pa owó wọlé.  Dipò ki wọn lo owó ti ó wọlé lati tú ilú ṣe, wọn bẹ̀rẹ̀ si pin owó lati fi ra owó Òkè-Òkun lati kó jade lọ ra ilé nlá si àwọn ilú wọnyi lati sá fún ilú ti wọn bàjẹ́ ni gbogbo ọ̀nà.

Owó epo rọ̀bì fọ́, awọ kò wá ká ojú ilú mọ́.  Oníṣẹ́ Ìjoba kò ri owó-oṣ̀ù gbà déédé, àwọn ti ó fi ẹhin ti ni iṣẹ́ Ìjọba kò ri owó ifẹhinti wọn gba, owó ilú bàjẹ́, bẹni àwọn Òṣèlú bú owó oṣ́u rẹpẹtẹ fún ara wọn.  Eyi ti ó burú jù ni owó rẹpẹtẹ miran ti wọn bù lati ra ọkọ ti ìbọn ò lè wọ, olówó nla lati Òkè-Òkun fún Ọgọrun-le-mẹsan Aṣòfin-Àgbà.   Olóri Aṣòfin-Àgbà fẹ ra ọkọ̀ mẹsan fún ara rẹ nikan.

Àsìkò tó ki àwọn èrò ji lati bá àwọn olè wọnyi wi, nitori àwọn Òṣèlú Òkè-Òkun nibiti wọn nkó owó ilú lọ, kò fi owó ilú wọn tọ́jú ara wọn, wọn nwọ ọkọ̀ pẹ̀lú àwọn ará ilú, àyè kò si fún wọn lati ja ilú ni olè bi ti àwọn Òṣèlú Nigeria.

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button

Originally posted 2016-02-19 10:12:16. Republished by Blog Post Promoter

“Òṣèlú Nigeria, Ẹ Jọ̀wọ́, Ẹ Má Pe Ajá ni Ọ̀bọ fún Ará Ìlú” – “Pleading with the Nigerian Politicians to stop calling a dog, a monkey for the people”

Lati bi ogójì ọdún sẹhin, Epo-rọ̀bi nikan ni okùn ọrọ̀ ajé orilẹ̀ èdè Nigeria, ó si ti pa owó ribiribi wọlé fún ilú.  Nigbati Epo-rọ̀bi bẹ̀rẹ̀ si pa owó wọlé, ará ilú kọ iṣẹ́ àgbẹ̀ àti àwọn ohun ti ilú nṣe silẹ̀ fún ifẹ́ ọjà òkèrè.  Àsikò Epo-rọ̀bi ni ilú fi irẹsi òkèrè dipò oriṣiriṣi oúnjẹ ilẹ̀ wa.  Ki ṣe eyi nikan, Ìjọba Ológun àti Òṣèlú bẹ̀rẹ̀ iwà ibàjẹ́ nipa ki kó owó ti ó yẹ ki wọn fi tún ilú ṣe jẹ.  Wọn ò kó owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ yi dúró ni ilú, wọn nko lọ si Òkè-Òkun, eyi ló ba iná mọ̀nàmọ́ná, ilé-ìwòsàn, ilé-iwé, ọ̀nà, omi mi-mun àti ohun amáyédẹrùn yoku jẹ́.

Lẹhin ti àwọn Ìjọba Ológun àti Òṣèlú fi ipò wọn ba ilú jẹ́ tán, bi ori bá fọ́ wọn, wọn á gba ọ̀nà Òkè-Òkun lọ fún ìtọ́jú, dipò ki wọn tú ile-iwé ṣe, wọn a fi owó ti wọn ji pamọ́ rán ọmọ lọ si Òkè-Òkun fún ẹ̀kọ́ ti ó yè kooro.  Wọn a fi owó àbẹ̀tẹ́lẹ́ ra ilé nla si Òkè-Òkun, oúnjẹ àti èso ilú kò dùn lẹnu olówó, aṣọ àti ohun ti ará ilú nṣe kò dára tó, ọjà Òkè-Òkun nikan ni wọn lè fi yangàn.

Lai pẹ yi, àwọn Òṣèlú bẹ̀rẹ̀ si polongo pé “ki ará́ ilu ra ọja ilú, ki Naira (owo Nigeria) lè gòkè”.  Ki i ṣe ìyànjú burúkú ni eyi ṣùgbọ́n, “ọ̀rọ̀ kò dùn lẹ́nu olè”,  kì í ṣe lati ẹnu àwọn Òṣèlú ti ẹnu wọn ti fẹ si ọjà òkèrè nitori wọn ti kó owó ilú pamọ́ si àwọn ilú Òkè-Òkun.  Bi a bá ṣe akiyesi, ki àṣiri tó tú ni àsikò Ìjọba tuntun (Buhari/Òṣinbàjò), àwọn ti ilé-iṣẹ́ Agbógun ti ìwà ìbàjẹ́ tọka tàbi mú pé ó kó owó ilú jẹ jù̀, kò wọ aṣọ Òkè-Òkun.  Ó san ki wọn wọ aṣọ Òkè-Òkun, ju ki wọn kó owó rẹpẹtẹ ti wọn ji kó lọ si Òkè-Òkun.

Díẹ̀ ninú àwọn Òṣèlú ti Ilé Iṣẹ́ Agbógun ti Ìwà Ìbàjẹ́ fi ẹ̀sùn kàn: Some of the Politicians facing corrupt charges by Economic and Financial Crimes Commission (EFCC)

Ẹ̀bẹ̀ la bẹ̀ “Òṣèlú Nigeria” ki wọn ma pe Ajá l’Ọbọ fún ará ilú, ki wọn kó owó ilú ti wọn ji pamọ́ si Òkè-Òkun padà, ki wọn si fi àpẹrẹ rere silẹ̀ fún ará ilú nipa àyipadà kúrò ni iwà ojúkòkòrò àti olè ti wọn nfi ipò jà dúró.  Àyipadà Òṣèlú kúrò ninú iwà burúkú ni ó lè mú ki owó ilú (Naira) kògè.

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button