Tag Archives: Economic activities paralysed in Nigeria

“Dúró ninú odò tó dé orókún, sunkún òùngbẹ”: Ọ̀wọ́n epo ọkọ̀ ní Nigeria – “Standing Knee deep in a River dying of thirst”: Fuel Scarcity in Nigeria

Ki i ṣe àkọ́kọ́ ti ọ̀wọ́n epo ọkọ̀ yio wáyé ni Nigeria, ṣùgbọ́n bi ijiyà ti ọ̀wọ́n epo ọkọ̀ kó bá ará ilú bá ti tán, Ìjọba àti ará ilú á gbàgbé ni wéré, wọn ki kọ́ ọgbọ́n lati ronú ohun ti wọn lè ṣe lati jẹ ki irú rẹ ma wáyé mọ.

Epo ọkọ̀ kò kọ́kọ́ wọ́n nigbati Olóri-ogun Abacha gba Ìjọba ni ọdún mejilélógún sẹhin, ṣùgbọ́n lati bi ogún ọdún, epo ọkọ̀ bẹ̀rẹ̀ si wọn ni ilé-epo nitori wọn kò tún ilé iṣẹ́ tó nṣe epo ọkọ̀ ṣe, àbẹ̀tẹ́lẹ̀ gbigbà àti iwà ibàjẹ́ pọ̀ fún àwọn ti o nkó epo ọkọ̀ wọlé lati Òkè-òkun àti ilé-epo.  Ijiyà yi pọ gidigidi, nitori ọ̀pọ̀ n sun ilé-epo fún ọ̀sẹ̀ kan nitori àti ri epo ọkọ̀ rà ni oye ti Ìjọba ni ki wọn ta a, ṣùgbọ́n ilé epo gbà lati ta epo fùn alarobọ̀ ju ọlọ́kọ̀ lọ.  Nigbati Olóri-ogun Olúṣẹ́gun Ọbásanjọ́ di Olóri-Òṣèlú, ti wọn ri ọ̀rọ̀ ọ̀wọ́n epo ọkọ̀ yanjú, ilú gbàgbé iyà yi.  Yàtọ̀ si ki àwọn Ọlọ́kọ̀ epo ọkọ̀ da iṣẹ́ silẹ̀, tàbi ki òṣiṣẹ́ ilé-epo rọ̀bì da iṣẹ́ silẹ̀, ọ̀wọ́n epo ti fẹ́ di ìgbàgbé, nitori irú eleyi ki pẹ́ ju ọjọ́ meji si mẹta lọ.

Ẹ ṣe iránti, ni oṣù kini ọdún kẹta sẹhin, nitori wọn fẹ fi owó kún epo ọkọ̀ lójú ẹ̀rọ, epo ọkọ̀ wọ́n, ṣùgbọ́n bi ilú fẹ́ bi ó kọ̀, Ìjọba Goodluck Ebele Jonathan fi owó kún epo ọkọ̀ lati Naira marunlelọgọta di Naira mẹtadinlọgọrun.  Ni àsìkò yi, gbogbo èrò bọ́ sita lati sọ tinú wọn pé kò si ohun ti ó yẹ ki wọn gbé epo rọ̀bi lati Nigeria lọ si Òkè-Òkun lati lọ sọ di epo ọkọ̀, ki wọn tún fi owó ko padà silé pẹ̀lú owó iyebiye nigbati wọn lè tún ilé-iṣẹ́ to nṣe epo ọkọ̀ ṣe àti lati kọ́ tuntun si.  Ìjọba ṣe ìlérí fún ará ilú pé àwọn yio lo owó ti wọn bá ri fi tún ohun amáyédẹrùn igbàlódé ṣe, wọn o si kọ àti tún ilé-iṣẹ́ ti o nsọ epo rọ̀bì di epo ọkọ̀ ṣe.  Ọdún mẹta ti kọjá, Ìjọba kò mú ìlérí yi ṣẹ nitori àbẹ̀tẹ́lẹ̀ gbigbà àti iwà ibàjẹ́.  Continue reading

Share Button