Tag Archives: Chief Obafemi Awolowo

“À ì sí Iná Mọ̀nà-mọ́ná àti Epo Ọkọ̀ bá Onílé pẹ̀lú Àlejò”: – “Everybody is affected by lack of electricity and petroleum scarcity”

Ki gbogbo Nigeria tó gba ominira ni àwọn Òṣèlú lábẹ́ olùdari Olóyè Ọbáfẹ́mi Awolọwọ ti fi owó kòkó àti iṣẹ́-àgbẹ̀ dá nkan ṣe fún gbogbo ilẹ̀ Yorùbá.  Yorùbá jẹ èrè àwọn ohun gidi, amáyé-dẹrùn bi ilé-iwé ọ̀fẹ́, ilé-ìwòsàn ọ̀fẹ́, ilé iṣẹ́ amóhùn-máwòrán àkọ́kọ́, ilé àwọn àgbẹ̀ (olókè mẹrin-lé-lógún – ilé giga àkọ́kọ́), ọ̀nà ọlọ́dà, omi, iná mọ̀nà-mọ́ná àti bẹ́ẹ̀bẹ́ẹ̀ lọ.  Àwọn ohun ipèsè wọnyi jẹ èrè lati ọ̀dọ̀ Òṣèlú tó fẹ́ràn ilú ti ó gbé wọn dé ipò, eleyi jẹ àwò kọ́ iṣe fún àwọn Òṣèlú ẹ̀yà ilẹ̀ Nigeria yókù.

Ìjọba Ológun fi ibọn àti ipá gbé ara wọn si ipò Òṣèlú, wọn fi ipá kó gbogbo ohun amáyé-dẹrùn si abẹ́ Ìjọba àpapọ̀.  Lati igbà yi ni ilé-iwé kékeré àti giga, ilé-ìwòsàn àti ohun amáyé-dẹrùn ti Òṣèlú pèsè fún agbègbè wọn ti bẹ̀rẹ̀ si bàjẹ́.  A lè fi ibàjẹ́ ohun amáyé-dẹrùn ti àwọn Òṣèlú àkọ́kọ́ pèsè fún ara ilú wọnyi wé ọbẹ̀ tó dànu,̀ ti igbẹhin rẹ já si òfò fún onilé àti àlejò.

Òwe Yorùbá ni “Ọbẹ̀ tó dànù, òfò onilé, òfò àlejò” Àpẹrẹ pataki ni ọna àti ilé-iwosan ti ó bàjẹ́.  Òfò ni ọ̀nà ti ó bàjẹ́ mú bá ara ilú nipa ijàmbá ọkọ̀ fún onilé àti àlejò.  Ibàjẹ́ ile-iwosan jẹ òfò fún onilé àti àlejò nitori ọ̀pọ̀ àisàn ti kò yẹ kó pani ló ńṣe ikú pani, fún àpẹrẹ, itijú ni pé, Ọba, Ìjòyè àti Òṣèlú ńkú si àjò fún àìsàn ti kò tó nkan.  Dákú-dáji iná mọ̀nà-mọ́ná ti ó sọ ilú si òkùnkùn jẹ́ òfò fún olówó àti aláini nitori, yàtọ̀ si ariwo àti òórùn, ai mọye enia ni ikú ẹ̀rọ mọ̀nà-mọ́ná ti pa. À ì sí Iná Mọ̀nà-mọ́ná àti Epo Ọkọ̀ bá Onílé pẹ̀lú Àlejò.  Ìwà ìbàjẹ́, àbẹ̀tẹ́lẹ̀ gbi gbà fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ló da ọbẹ̀ ohun amáyédẹrùn danu.

Bi ọbẹ̀ bá dànù, kò ṣe kó padà, à fi ki enia se ọbẹ̀ tuntun, bi ó bá fẹ jẹ ọbẹ̀.  Yorùbá ni “Ẹ̀bẹ̀ là nbẹ òṣikà, ki ó tú ilú ṣe”.  Fún àtúnṣe, ó ṣe pàtàki ki gbogbo ará ilú parapọ̀ lati tún ohun ti ó ti bàjẹ́ ṣe nipa gbi gbé ogun ti iwà ìbàjẹ́ àti àbẹ̀tẹ́lẹ̀ gbi gbà.

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button

Originally posted 2016-04-08 11:31:39. Republished by Blog Post Promoter

“A kì í tó́ó báni gbé, ká má tòó ọ̀rọ̀-ọ́ báni sọ” – Ìdàpọ̀ Àríwá àti Gũsu Nigeria: – 1914 Amalgamation of the Northern and Southern Nigeria

Ó pé ọgọrun ọdún ni ọjọ́ kini, oṣù kini ọdún Ẹgba-̃le-mẹrinla ti Ìjọba Ìlú-Ọba ti fi aṣẹ̀ da Àríwá àti Gũsu orílẹ̀ èdè ti a mọ̀ si Nigeria pọ.  Ìjọba Ìlú-Ọba kò bere lọwọ ará ilú ki wọn tó ṣe ìdàpọ̀ yi, wọn ṣe fún irọ̀rùn ọrọ̀ ajé ilú ti wọn ni.

Yorùbá ni “À jọ jẹ kò dùn bi ẹni kan kò ri”.  Ni tõtọ, Ijọba Ilu-Ọba ti fún orilẹ̀ èdè Nigeria ni ominira, ṣùgbọ́n èrè idàpọ̀ ti ará ilú kò kópa ninu rẹ kò tán.  Gẹgẹbi Olóyè Ọbafẹmi Awolọwọ ti sọ nigbati wọn ńṣe àdéhùn fún ominira pe: “ominira ki ṣe ni ti orúkọ ilú lásán, ṣùgbọ́n ominira fún ará ilú.  A ṣe akiyesi pe lẹhin ìdàpọ̀ ọgọrun ọdún, orilẹ̀ èdè ko ṣe ikan.

Yorùbá ni “A kì í tó́ó báni gbé, ká má tòó ọ̀rọ̀-ọ́ báni sọ” Gẹgẹbi òwe yi, ki ṣe ki kó ọ̀kẹ́ aimoye owó lati ṣe àjọyọ̀ ìdàpọ̀ ti ará ilú kò kópa ninu rẹ ló ṣe pàtàki, bi kò ṣé pé ki a tó ọ̀rọ̀ bára sọ.

Yorùbá ni “Ọ̀rọ̀ la fi dá ilé ayé”.  Bi ọkọ àti iyàwó bá wà lai bára sọ̀rọ̀, igbéyàwó á túká, nitori eyi, ó ṣe pàtàki ki gbogbo ara ilú Nigeria lápapọ̀ ṣe àpérò bi wọn ti lè bára gbé ki ilú má bã túká.

ENGLISH TRANSLATION

“One does not qualify to live with a person without also qualifying to talk to the person” – Amalgamation of the Northern and Southern Nigeria Continue reading

Share Button

Originally posted 2014-01-07 23:11:15. Republished by Blog Post Promoter