Ìbà Àkọ́dá – Reverence to the First Being

Obinrin ti ó́ nṣe Ì̀bà Aṣẹ̀dá - A woman paying reverence to the Creator. Courtesy: @theyorubablog

Obinrin ti ó́ nṣe Ì̀bà Aṣẹ̀dá – A woman paying reverence to the Creator. Courtesy: @theyorubablog

Ìbà Àkọ́dá, ìbà Aṣẹ̀dá
Ìbà ni n ó f’òní jú, mo r’íbà, k’íbà ṣẹ
Nínú ríríjẹ, nínú àìríjẹ
Mo wá gbégbá ọpẹ́, mo r’íbà k’íbà ṣẹ
Alápáńlá tó so’lé ayé ró
Ṣe àtúntò ayé mi
Ní gbogbo ọ̀nà tí mo ti k’etí ikún sí Ọ
Baba d’áríjì, mo bẹ̀bẹ̀
Odò Orisun Rẹ ni mí, máṣe jẹ́ n gbẹ

Ìbà! ìbà!!

Ọmọ ìkà ń d’àgbà, ọmọ ìkà ń gbèrú
Ọmọ ẹni ire a má a tọrọ jẹ
Ọmọ onínúure a má a pọ́njú
Bó ti wù Ọ ́lo ń ṣ’ọlá Rẹ
Ìṣe Rẹ, Ìwọ ló yé o; Ògo Rẹ, é dibàjẹ́
Àpáta ayérayé, mo sá di Ọ ́o
Yọ́yọ́ l’ẹnu ayé
Aráyé ń sọ Ọ ́sí láburú, aráyé ń sọ Ọ ́sí rere
Ọlọ́jọ́ ń ka’jọ́
Bó pẹ́, bó yá, ohun ayé á b’áyé lọ

Ìbà! ìbà!!

Ẹni iná ọ̀rẹ́ bá jó rí, bó bá ní’hun nínú kò ní lè rò
ọ̀rẹ́ gidi ń bẹ bíi ká f’ẹ́ni dé’nú
ọ̀rẹ́ ló ṣe’ni l’ọ́ṣẹ́ tó ku s’ára bí iṣu
Ìrètí nínú ènìyàn, irọ́ funfun gbáláhú!
ọ̀rẹ́ kan tí mo ní
Elédùmarè, Alágbára, ìbà Rẹ o Baba, Atóbijù!

Ìbà! ìbà!!

ENGLISH TRANSLATION

Reverence to the First Being, reverence to the Creator
I will revere Him today; let my reverence be
In times of plenty, in times of scarcity
I come with a heart of thanksgiving; let my reverence be
The One Whose mighty hand holds the world sway
Order my life
In ways I’ve been disobedient to You
Father, forgive me, I pray
I’m the river that flows from Your Source; do not let me dry up

Reverence! Reverence!!

The wicked grow, the wicked prosper
The good beg for food
The kind suffer
You do as You please
Your mysterious ways are known only to You; Your glory never tarnishes
The Rock of Ages, I look to You
Man’s wagging tongue is never reliable
Man speaks ill of You; man speaks good of You
The One Who has the days keeps numbering them
Sooner or later, the things of the world will perish with the world

Reverence! Reverence!!

He who gets burnt by a friend’s fire of betrayal keeps what he has in his mind to himself
There is a true friend as such that loves you deeply
There is also such a friend that kills in betrayal
Hope entrusted in man is a blatant lie!
The One Friend I have
God, The Almighty, I reverence You; Father, You’re the Greatest!

Reverence! Reverence!!

*Culled from my song “ÌBÀ”.

Share Button

Originally posted 2015-10-02 19:50:39. Republished by Blog Post Promoter

This entry was posted in Learning Yoruba, Yoruba Community, Yoruba Culture, Yoruba Folklore, Yoruba for the young, Yoruba Proverbs and tagged , , , on by .

About Adéṣọlá

Adéṣọlá is a writer, songwriter, poet and a music addict who has undeniable love and passion for the music more than the industry. That same passion he has endears him to the booth, finally spurring him on into deciding to cut his teeth in the art he truly treasures. Even though he started out as a rapper with strict reservations for Hiphop, he couldn't avoid been drawn back to his music background spanning across various music genres of Soul, R&B, Rock, Jazz, Juju, Fuji, etc. just to mention a few. Having a talent for singing, rather than being confined to rapping alone, he decided to explore his gift. His type of music is Inspirational and Urban Contemporary and his in-depth style of songwriting and Yorùbá roots often reflect in his songs. "I like to speak about life issues. I love to sing about God, life and love; issues that concerns everybody." He's a Nigerian.

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

Time limit is exhausted. Please reload the CAPTCHA.