“Ẹni àjò ò pé, kó múra ilé” – “Ìjà Boko Haram” – The person for whom a journey has not been profitable, should prepare to return home – “Boko Haram mayhem”

Yorùbá jẹ́ ẹ̀yà ti ó wà ni Ìwọ̀-õrùn orilẹ̀ èdè Nigeria.  Bi Yorùbá ti fẹ́ràn igbádùn tó, bẹ ni wọn fẹ́ràn òwò ṣiṣe àti ẹ̀kọ́ kikọ́.  Ọba, Olóyè, Ọlọ́rọ̀ àti aláìní ilẹ̀ Yorùbá ló fẹ́ràn àti rán ọmọ wọn lọ si ilé-iwé bi àwọn fúnra wọn kò ti ẹ lọ si ilé-iwé. Eleyi jẹ ki Yorùbá pọ kà kiri àgbáyé pàtàki ni Àríwá/Òkè-ọya Nigeria.

Nibi ti ọ̀pọ̀lọpọ̀ Yorùbá ti fẹ́ràn “iwé-kikà” ni ẹ̀yà miràn ti fi ẹsin bojú lati ṣe àtakò iwé kikà, pàtàki àwọn ti o ni “A ò fẹ́ iwé – Boko Haram”.   Àwọn ti ó ni àwọn kò fẹ́ lọ si ilé-iwé bẹ̀rẹ̀ si pa ọmọ àwọn ti ó fẹ́ lọ.  Wọn kò dúró lóri ọmọ ilé-iwé nikan, wọn ńpa enia bi ẹni pa ẹran ni ọjà, oko, ilú, ọ̀nà àti gbogbo ibi ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ilú ni òkè-Ọya pàtàki ni ilú “Borno”.

Girls kidnapped from Nigeria school

Islamic militants suspected in Nigeria abduction of 100 female students

Yorùbá ni “Bi onilé bá ti ńfi àpárí iṣu lọ àlejò, ilé tó lọ”.  Ki ṣe àpárí iṣu nikan ni wọn fi ńlọ àjòjì ni òkè-ọya/Àriwá “ikú òjiji” ni.  Àini ifọkàn balẹ̀ kò lè jẹ́ ki àjò ò pé.  Lati igbà ti “ẹni ti ó so iná ajónirun mọ́ra” ti bẹ̀rẹ̀ si pa enia bi ẹni pẹran ni ilé ijọsin – pàtàki ti onígbàgbọ́; ọjà; ãrin ilú; abúlé àti ilé-iwé ni àjò kò ti pé mọ́. Ìròyìn kàn ni ọjọ́ kẹdogun oṣù kẹrin ọdún ẹgbã-lé-mẹrinla, pe wọn ti tún bẹ̀rẹ̀ si ji ọmọ ilé-iwé gbé – ó lé ni ọgọrun  ọmọ obinrin ti wọn fi ipá ji wọn gbé, mẹrinla ni ó ri àyè sá mọ́ ajínigbé lọ́wọ́, òbi àwọn ti ó kù wà ninú ìrora.

A lè fi òwe Yorùbá ti ó ni “Ẹni àjò ò pé, kó múra ilé” gba àwọn Yorùbá ti ó wà ni òkè-ọya ni ìyànjú pé ki wọn bẹ̀rẹ̀ si múra ilé, ki wọn ma ba pàdánù ẹmi, ó sàn ki enia pàdánù owó ju ẹ̀mi lọ.

ENGLISH TRANSLATION

Yoruba is an ethnic group in the Western part of Nigeria.  As much as Yoruba loves live so also do they love business/trading and education.  Yoruba Kings, Chiefs, wealthy people and the poor ones love to send their children to school even if they were not educated.  As a result of this, there are many Yoruba people all over the world, particularly in Northern Nigeria.

As Yoruba people are expressing their love for “education”, so also are some ethnic groups using religion as cover to attack schooling, particularly “Boko Haram meaning no Western education”.  These groups rejecting education are also preventing those who want to acquire education by attacking schools.  Their attack is not limited to schools, they kill people as if they are killing animals, in the market; farm; towns; on the road and many other cities in the Northern part of Nigeria particularly in “Borno”.

Yoruba said “When the host is passing the head of yam to the visitor, it is time for the visitor to leave”.  It is not only the bitter head of yam that is being passed to the strangers in the North – “it is untimely death”.  Lack of peace cannot make the strangers to settle in.  The journey has not been profitable since the surge of “suicide bombers” that have been killing people like animals in the place of worship – particularly Churches; markets; town centres; villages and schools.  The news that the Islamist group have begun to kidnap was broken on the fifteen of April, 2014, as more than hundred female students were abducted, only fourteen managed to escape from the abductors while parents of the remaining students are still in pain.

Yoruba proverb as translated by Oyekan Owomoyela that said “The person for whom a journey has not been profitable, should prepare to return home” is apt as this can be used to advice Yoruba people in the Northern part of Nigeria to begin preparation to return home to avoid loss of their lives as it is better to lose business/money than live.

Share Button

Leave a Reply

Your email address will not be published. Required fields are marked *

Time limit is exhausted. Please reload the CAPTCHA.