Category Archives: Yoruba related News

Yoruba related news…

A kú Ìdùnnú Ìdúpẹ́ – Happy Thanksgiving

Bi Ọlọrun ti ńdárí ẹ̀ṣẹ̀ ji èniyàn
Bi Olóri Òṣèlú Àmẹ́rikà ti ńdáríji tòlótòló
Bẹni ki èniyàn dári ji ẹni ti ó bá ṣẹ́, nitori ki a lè fi ìdùnnú dúpẹ́.

Olóri Òṣèlú Àmẹ́rikà dáríji tòlótòló – American President pardons the Turkey during Thanksgiving

 

 

Share Button

Ikú kò mọ àgbà, ó mú ọmọdé bi Jidé Tinubu – Death is no respecter of age, Jide Tinubu was snatched away by death

Òwe Yorùbá sọ wi pé “bi iná bá kú, á fi eérú bojú, bi ọ̀gẹ̀dẹ̀ bá kú, á fi ọmọ ẹ rọ́pò”.  Òwe yi fi hàn ipò ti Yorùbá fi ọmọ si.  Kò si ẹni ti kò ni kú, ṣùgbọ́n ọ̀fọ̀ nlá ni ikú ọmọ jẹ́ fún òbí àti àwọn ti olóògbé bá fi silẹ̀ pàtàki àbíkú àgbà.  Ìròyìn ikú Jidé Tinubu àrólé Gómìnà Èkó tẹ́lẹ̀ Aṣíwájú Bọ́lá Ahmed Tinubu kàn pé ó jade láyé ni Ọjọ́rú, ọjọ́ kini oṣù kọkànlá ọdún Ẹgbàálémẹ́tàdínlógún.

Góm̀nà tẹ́lẹ̀ Bọla Tinubu pẹ̀lú ìyàwó Rẹ̀mí àti ọmọ rẹ olóògbé Jidé nigbà ayẹyẹ ìwé-ẹri Agbejọ́rò – former Gov Tinubu with his wife Remi and late son Jide during his Law School graduation

Ọlọrun ki ó dáwọ́ àbíkú àgbà dúró, ki ó si tu bàbá olóògbé,  Gómìnà Èkó tẹ́lẹ̀ Aṣíwájú Bọ́lá Ahmed, ìyàwó, àwọn ọmọ àti gbogbo ẹbí ninú.  Ki Èdùmàrè dá ikú ọ̀dọ́ dúró, kó tu gbogbo àwọn ti irú ọ̀fọ̀ bẹ́ ẹ̀ bá ṣẹ̀ ninú.

ENGLISH TRANSLATION

According to one of the Yoruba proverbs translated thus “fire is succeeded by ashes, plantain/banana is replaced by its fruits”.  This proverb reflects the hope Yoruba placed on their children. Death is unavoidable by everyone, however, the death of one’s child is often a terrible bereavement for the parents of the deceased particularly the death of an adult child.  On Wednesday, November 1, 2017, the news of the death of Jide Tinubu the first son of the former Governor of Lagos State, Bola Ahmed Tinubu was announced. Continue reading

Share Button

Ìròyìn kàn pé Ọ̀túnba Gani Adams ni Aàrẹ Ọ̀na Kakanfo Yorùbá karùndinlógún – Chief Gani Adams has been announced as the Fifteenth Generalissimo of Yorubaland

Ọba Lamidi Adéyẹmi àti Ọ̀túnba Gani Adams – Aláafin Lamidi Adeyemi & Chief Gani Adams

Lẹhin ọdún kọkàndinlógún ikú Olóògbé Olóyè M.K.O Abíọ́lá, Aàrẹ Ọ̀na Kakanfo Yorùbá kẹ̀rinlá, Ọba Lamidi Adéyẹmi yan Ọ̀túnba Gani Adams si ipò Aàrẹ Ọ̀na Kakanfo Yorùbá karùndinlógún.

Ọ̀túnba Gani Adams ni olùdásílẹ̀ Ẹgbẹ́ Ọ̀dọ́ Ọmọ Oòduà, ti wọn dá silẹ̀ ni ọjọ́ karùndinlọ́gbọ̀n, oṣù kẹjọ ọdún kẹtàlélógún sẹhin ni Mushin, lati jà fún gbi gbé ipò Olórí Òṣèlú fún M.K.O Abiola ti ó mókè ni ìbò ti wọn di ni ọjọ́ kejila ọdún kẹrinlélógún sẹhin lai si ìjà tàbi asọ̀ ni gbogbo orílẹ̀ èdè Nigeria.  Kò bojú wẹ̀hin lati ọdún kẹtàlélógún lati má a jà fún Yorùbá lati gba ẹ̀tọ́, iyì àti gbi gbé àṣà Yorùbá ga kakiri àgbáyé.  Fún akitiyan yi, wọn ti fi jẹ oyè mejilelaadọta kakiri, ṣùgbọ́n adé gbogbo oyè yi ni Aare Ona Kakanfo.

Bi àwọn alatako diẹ ti wa ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ àgbàgbà Yorùbá ti fi ọwọ́ si yin yan Ọ̀túnba Gani Adams si ipò Aare Ona Kakanfo karundinlogun.  Lára àwọn enia pàtàki ti ó ki kú ori ire ni, Ọọni Ifẹ̀, Gómìnà Bọ́la Tinubu, Gómìnà Rauf Arẹ́gbẹ́sọlá, àwọn ọ̀gá olórin àti bẹ́ ẹ̀ bẹ́ ẹ̀ lọ.

Olùkọ̀wé Yorùbá lóri Ayélujára kí Ọ̀túnba Gani Adams kú ori ire, oyè á mọ́rí o, ẹ ò ni kú léwe, ẹmi ọlá á gùn lati má a jà fún Yorùbá àti lati gbé àṣà Yorùbá lárugẹ si, ni gbogbo àgbáyé.

ENGLISH TRANSLATION

Nineteen years after the death of Chief M.K.O. Abiola, the fourteenth Generalissimo of Yorubaland, the Alafin of Oyo, Oba Lamidi Adeyemi has nominated Chief Gani Adams as the 15h Generalissimo of Yorubaland.

Chief Gani Adams was the founder of the Odua Youth Movement which was formed on August 25, 1994 at Mushin, Lagos, to fight for the actualisation of June 12, 1993 Presidential election won by Chief M.KO. Abiola in a free and fair election all over Nigeria.  He has not looked back since he came to prominence in 1994 as he continued to fight to uphold the dignity, honour and culture of his people.  His action of defending and promoting Yoruba culture has earned him fifty-two titles but the crown of all the titles is the Aare Ona Kakanfo.

Although there are some oppositions, many prominent Yoruba leaders have endorsed the nomination of Otunba Gani Adams as the fifteen Aare Ona Kakanfo.  Prominent among them are, Ooni of Ife, Governors – Ahmed Bola Tinubu (former Governor of Lagos State), Rauf Aregbesola (Osun State Governor), prominent Musicians etc.

The Yoruba Blog congratulates Chief Gani Adams and pray that he will not die young but live long to continue in the service of defending Yorubaland and promoting her culture all over the world.

Share Button

Adébáyọ̀ Fálétí, ògúná gbòngbò ti ó gbé èdè àti àṣà Yorùbá lárugẹ jade láyé: A Prominent Yoruba language and Culture promoter has departed the world

Àwọn iwé ìròyìn gbe jade wi pé Adébáyọ̀ Fálétí, ògúná gbòngbò ninú àwọn ti ó gbé èdè àti àṣà Yorùbá lárugẹ ni àgbáyé, re ibi àgbà nrè ni ọjọ́ ìsimi ọjọ́ kẹtàlélógún, oṣù keje, ọdún Ẹgbàálémẹ́tàdinlógún.  Ọmọ ọdún mẹrindinlaadọrun ni olóògbé Fálétí ki wọn tó jade láyé.

Olóògbé Adébáyọ̀ Fálétí relé – Late Adebayo Faleti has gone home.

Ni ìgbá ayé olóògbé Adébáyọ̀ Fálétí, ó jẹ́ ìkan ninú àwọn òṣìṣẹ́ àkọ́kọ́ ni ilé iṣẹ́ amóhùn-máwòrán àkọ́kọ́ ni ilẹ̀ Aláwọ̀dúdú ti wọn dá sílẹ̀ ni Ìbàdàn ti ó jẹ́ olú ilú ẹ̀yà Yorùbá ni ìwọ̀ oòrùn orílẹ̀ èdè Nigeria.  Ó gbé èdè Yorùbá lárugẹ nipa ṣi ṣe iṣẹ́ ìtumọ̀ èdè Gẹ̀ẹ́sì si èdè Yorùbá, ó kọ ìwé itumọ̀ ọ̀rọ̀ nipa li lo orúkọ Yorùbá.  Kò tán síbẹ, oníròyìn ni, ó fi eré ìtàgé gbé èdè Yorùbá lárugẹ nipa di dá ẹgbẹ́ ọ̀dọ́ Ọ̀yọ́ fún ìgbéga eré ìtàgé silẹ̀ ni ọdún mejidinlaadọrin sẹhin.  Lára àwọn eré Yorùbá ti olóògbé Adébáyọ̀ Fálétí kọ, ti ó si ṣe ni “Mágùn, Àfọ̀njá, Baṣọ̀run Gáà àti bẹ́ ẹ̀ bẹ́ ẹ́ lọ.

Ẹ̀kọ́ pọ̀ fún ọ̀dọ́ ayé òde òní lati kọ́ lára ìgbésí ayé olóògbé Adébáyọ̀ Fálétí.  Lára ẹ̀kọ́ yi ni wi pe, ìwé kí kà ṣe pàtàkì, bi kò ti ẹ̀ si ìrànlọ́wọ́ lati ka ìwé ni ọmọdé, bi enia bá ka ìwé ni àgbà yio wúlò.  Olóògbé Adébáyọ̀ Fálétí padà si ilé-ìwé  lati lọ pari ìwé mẹfa ti ó dá dúró nigbati kó si agbára fún bàbá rẹ.  Lẹhin eyi ó fi àgbà ara ka ìwé ni ilé-ìwé ẹ̀kọ́ giga.  Ó gbé ìgbésí ayé rere nipa ìtọ́jú àwọn ọmọ àti ìyàwó, ó si fún àwọn ọmọ ni ẹ̀kọ́ ilé àti ti ilé-ìwé.

Fún àwon iṣẹ́ ribiribi yi, olóògbé Adébáyọ̀ Fálétí gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹ̀bùn àpínfún ni orilẹ̀ èdè Nigeria àti ni òkè-òkun.

ENGLISH TRANSLATION

Many Nigerian Newspapers broke the news of the death of Adebayo Faleti, a prominent promoter of Yoruba language and culture on Sunday, 23rd day of year 2017.  He was 86 years at the time he departed the world.

During his lifetime, he was one of the pioneering staff of the Western Nigeria Television (WNTV) at Ibadan capital of Western State of Nigeria and the first of its kind in Africa.  He promoted Yoruba language as a Translator of English to Yoruba, he wrote a book on the meaning and use of Yoruba names.  That was not all, he was a Broadcaster and he used acting to promote Yoruba language and culture by establishing the ‘Oyo Youth Operatic Society’ sixty eight years ago.  Among the plays he wrote and acted in were ‘Magun, Afonja, Basorun Gaa’ etc.

The youths of nowadays have many lessons to learn from the life of late Adebayo Faleti.  Among such lessons, were the importance of education, even when there was no opportunity at a younger age, going to school as a later life learner often becomes very useful.  Late Adebayo Faleti returned to school at a later age to complete his primary school education which was hindered as a result of the father not being able to afford it. After completing primary six, he continued higher education as a later life learner.  He lived a life worthy of emulation by being responsible, caring for his children and wives and he gave his children formal and informal education.

Late Adebayo Faleti bagged many awards in Nigeria and abroad as a recognition of his immense contribution.

Share Button

Ọdún wọlé dé, ẹ ṣọ́ra fún ewu àfọwọ́fà ti ọti àmu párà lè fà – End of Year Celebration is here, beware of attracted danger caused

Ẹ kú àsikò yi o.  Bawo ni ipalẹ̀mọ́ ọdún Kérésìmesì àti ọdún titun?

Ni àsikò ọdún, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ma nfi oúnjẹ  àjẹ jù àti ọti à mu para yọ ayọ̀ ọdún.  Ni òtitọ́, ará ilú nké pé kò si owó àti ọ̀wọ́n ọjà, nitori eyi ayé àjẹ jù le ma si, ṣùgbọ́n bi ẹlòmíràn kò ni owó, á gba àwin ọti pé àwọn fẹ́ fi pa irònú rẹ́.  Àwọn miran nlo egbò igi olóró ti á gbọ́ wi pé ó ti wọ́pọ̀ ni orilẹ̀ èdè Nigeria pàtàki laarin àwọn ọ̀dọ́.  À fọwọ́ fà ni gbogbo eyi.

Kò si iyàtọ̀ laarin ọlọ́tí pẹ̀lú ẹni ti ó mu egbò igi olóró àti wèrè, nitori ihùwà ọlọ́ti àti ẹni lo oògùn olóró kò yàtọ̀ si ti wèrè bi wọn bá ti yó.  Bi ẹni ti ó mu àmu para àti ẹni lo egbò igi olóró bá wa ọkọ̀, àkóbá ni fún àwọn awakọ̀ yoku àti àwọn arin nà yoku.

Ki ọdún titun lè bá wa láyọ̀, ikilọ ni àsikò yi ni wi pé “Ki ẹni bá mú ọti tàbi ẹni tó lo egbò igi olóró ma ṣe wa ọkọ̀”.

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button

Ariwo Nigeria lóri èsi Idibo ni Amẹ́rikà: Nigerian’s noise on American Election Result

Èsi ibò ti wọn di ni ilú Amẹ́rikà ni oṣù kọkànlá, ọjọ́ kẹjọ jade ni òru ọjọ́ kẹjọ mọ́jú ọjọ́ kẹsan ọdún Ẹgbàálémẹ́rindinlógún.   Àwọn mẹta ti ó gbé àpóti ibò fún ipò olóri òṣèlú ni, Hillary Clinton, obinrin àkọ́kọ́ lati dé irú ipò bẹ́ ẹ̀ fún ẹgbẹ́ (Democrat), Donald J. Trump, Oniṣòwò nlá ti kò ṣe iṣẹ́ Ìjọba kankan ri fún ẹgbẹ́ (Republican) àti Gary Johnson fún ẹgbẹ́ kẹta (Libertarian).

Èsi ibò yi ya gbogbo àgbáyé lẹ́nu nitori àwọn ọ̀rọ̀ ti Donald Trump (Olóri ẹgbẹ́ GOP)  ti sọ siwájú nigbati ti ó polongo lati dé ipò.  Àwọn ọ̀rọ̀ iko rira wọnyi lòdi si àwọn obinrin, ẹ̀yà miran ti ó yàtọ̀ si ẹ̀yà rẹ, àlejò, ẹlẹ́sin Mùsùlùmi àti bẹ́ ẹ̀ bẹ́ ẹ̀ lọ.  Owe Yoruba so wipe “Bi Ẹlẹ́bọ kò bá peni, Àṣefín kò yẹni”.   Donald Trump ò ka gbogbo ilẹ̀ Aláwọ̀dúdú si nkankan tàbi dárúkọ Nigeria.  Ọ̀pọ̀lọpọ̀ rò wi pé nitori Amẹ́rikà ti nṣe Òṣèlú ti wa ntiwa fún igbalélógòji ọdún, ẹni ti wọn yio yan si irú ipò yi á ni iwà àkójọ àti ẹ̀mi àkóso si onírúurú àwọn enia ti ó wà ni gbogbo àgbáyé.

Ariwo Nigeria lóri èsi Idibo ni Amẹ́rikà: Nigerian Media's frenzy on US Election.

Ariwo Nigeria lóri èsi Idibo ni Amẹ́rikà: Nigerian Media’s frenzy on US Election.

Òwe Yorùbá ni “Bi èniyàn bá ni kò si irú òhun, àwọn ọlọ́gbọ́n a máa wòye”.  Lati igbà ti iròyin ibo ti jade pé Donald J. Trump ló wọlé, gẹ́gẹ́ bi wọn ti nṣe é, àwọn Olóri ilú àgbáyé ló kọ iwé tàbi pè lati ki ku ori ire.  Ó ṣe ni laanu wi pé, àwọn tó wà ni ilé aṣòfin Nigeria,  àti oriṣiriṣi àwọn Òṣèlú kékeré yókù lo nkọ iwé.  Gbogbo ìròyìn lati Nigeria kò ri ọ̀rọ̀ àti ìṣò̀ro ti ó dojú kọ ilú ti wọn sọ mọ, ju ọ̀rọ̀ èsi ibò ni Amẹ́rikà.  Eyi kò fi ọgbọ́n han nitori ìyà ti ó njẹ ará ilú Nigeria kọjá ki wọn ma sowọ́pọ̀ pẹ̀lú Olóri Òṣèlú Nigeria, Muhammadu Buhari lati ṣe àyipadà kúrò ni iwà ibàjẹ́ ti ó ba ilú jẹ, ki ilú lè tòrò, ki ó si lè pèsè oúnjẹ àti ohun amáyédẹrùn fún ará ilú.

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button

Muhammad Ali – Ọ̀gá pátápátá Afẹ̀ṣẹ́ kù bi Òjò àwọn Akànṣẹ́ Relé: “The Greatest Boxer” – Muhammad Ali has gone home

Worshipers and well-wishers take photographs as the casket with the body of the late boxing champion Muhammad Ali is brought for his jenazah, …

Ìròyìn ikú Muhammad Ali ọmọ ọdún mẹ́rinlélaadọrin kàn ni oṣù kẹfa, ọjọ́ kẹta, ọdún Ẹgbàálémẹ́rìndínlógún.  Bi ó ti ẹ jẹ wi pé, Ali ti wà lóri àisàn fún bi ọgbọ̀n ọdún, inú ọmọdé àti àgbà ni àgbáyé ṣe ìdárò nigbati wọn gbọ ìròyìn ikú rẹ.

Ki ṣe iṣẹ́ akànṣẹ́ nikan ni Muhammad Ali dúró fún, ó dúró fún ohun ti ó gbàgbọ́ lai bẹ̀rù.  Ni bi ọdún marun-dinlọgọta sẹhin, nigbati Aláwọ-funfun ṣe òfin lati ya Aláwọ̀-dúdú si ọ̀tọ̀, pé wọn kò lè lo ohun amáyédẹrùn (bi ọkọ̀ wi wọ̀ pọ̀, ilé oúnjẹ, ilé ìgbọ̀nsẹ̀ àti bẹ́ ẹ̀ b ẹ́ ẹ̀  lọ)  ti wọn pèsè fún ará ilú pẹ̀lú Aláwọ-funfun, Muhammad Ali kò pa ẹnu mọ lati dẹbi fún irú òfin àti iwà burúkú yi.  Ó kọ̀ lati lọ jagun (Vietnam), ti kò gbàgbọ́ nitori ó gbàgbọ́ pé alafia dára ju ogun lọ.  Muhammad Ali yi orúkọ ẹrú “Cacius Clay’’àti ẹ̀sìn padà lati kọ ẹ̀hin si iwà burúkú ti Aláwọ-funfun hù si enia rẹ.

Muhammad Ali mú adùn wọ iṣẹ́ akànṣẹ́, ó fi ọlà rẹ ṣe àánú fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ aláìní, ó si jẹ àwòkọ̀ṣe fún àwọn ọ̀dọ́ pàtàki Aláwọ̀-dúdú ti ó fi hà̀n pé ‘kò si ohun ti kò ṣe é ṣe, bi enia bá fi ọkàn si’.  Eleyi jẹ ki èrò fẹ́ràn rẹ púpọ̀.

Muhammad Ali and Joe Frazier – The Thrilla In Manila

Àwọn Olóri Ilú àti Ẹlẹ́sin ni oriṣiriṣi ati gbogbo àgbáyé ṣe ìdárò Muhammad Ali bi wọn ti ṣe ẹ̀yẹ ikẹhin tó yẹ fún Ọba, ni ibi ìtẹ́ ìsìnkú ni oṣù kẹfa, ọjọ́ kẹwa, ọdún Ẹgbàálémẹ́rìndínlógún.  Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọmọ, ọmọ-ọmọ, Ìyàwó, ẹbi àti ará ló gbẹ̀hin rẹ.  Sùn re o.

 

 

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button

“Òṣèlú Nigeria, Ẹ Jọ̀wọ́, Ẹ Má Pe Ajá ni Ọ̀bọ fún Ará Ìlú” – “Pleading with the Nigerian Politicians to stop calling a dog, a monkey for the people”

Lati bi ogójì ọdún sẹhin, Epo-rọ̀bi nikan ni okùn ọrọ̀ ajé orilẹ̀ èdè Nigeria, ó si ti pa owó ribiribi wọlé fún ilú.  Nigbati Epo-rọ̀bi bẹ̀rẹ̀ si pa owó wọlé, ará ilú kọ iṣẹ́ àgbẹ̀ àti àwọn ohun ti ilú nṣe silẹ̀ fún ifẹ́ ọjà òkèrè.  Àsikò Epo-rọ̀bi ni ilú fi irẹsi òkèrè dipò oriṣiriṣi oúnjẹ ilẹ̀ wa.  Ki ṣe eyi nikan, Ìjọba Ológun àti Òṣèlú bẹ̀rẹ̀ iwà ibàjẹ́ nipa ki kó owó ti ó yẹ ki wọn fi tún ilú ṣe jẹ.  Wọn ò kó owó àbẹ̀tẹ́lẹ̀ yi dúró ni ilú, wọn nko lọ si Òkè-Òkun, eyi ló ba iná mọ̀nàmọ́ná, ilé-ìwòsàn, ilé-iwé, ọ̀nà, omi mi-mun àti ohun amáyédẹrùn yoku jẹ́.

Lẹhin ti àwọn Ìjọba Ológun àti Òṣèlú fi ipò wọn ba ilú jẹ́ tán, bi ori bá fọ́ wọn, wọn á gba ọ̀nà Òkè-Òkun lọ fún ìtọ́jú, dipò ki wọn tú ile-iwé ṣe, wọn a fi owó ti wọn ji pamọ́ rán ọmọ lọ si Òkè-Òkun fún ẹ̀kọ́ ti ó yè kooro.  Wọn a fi owó àbẹ̀tẹ́lẹ́ ra ilé nla si Òkè-Òkun, oúnjẹ àti èso ilú kò dùn lẹnu olówó, aṣọ àti ohun ti ará ilú nṣe kò dára tó, ọjà Òkè-Òkun nikan ni wọn lè fi yangàn.

Lai pẹ yi, àwọn Òṣèlú bẹ̀rẹ̀ si polongo pé “ki ará́ ilu ra ọja ilú, ki Naira (owo Nigeria) lè gòkè”.  Ki i ṣe ìyànjú burúkú ni eyi ṣùgbọ́n, “ọ̀rọ̀ kò dùn lẹ́nu olè”,  kì í ṣe lati ẹnu àwọn Òṣèlú ti ẹnu wọn ti fẹ si ọjà òkèrè nitori wọn ti kó owó ilú pamọ́ si àwọn ilú Òkè-Òkun.  Bi a bá ṣe akiyesi, ki àṣiri tó tú ni àsikò Ìjọba tuntun (Buhari/Òṣinbàjò), àwọn ti ilé-iṣẹ́ Agbógun ti ìwà ìbàjẹ́ tọka tàbi mú pé ó kó owó ilú jẹ jù̀, kò wọ aṣọ Òkè-Òkun.  Ó san ki wọn wọ aṣọ Òkè-Òkun, ju ki wọn kó owó rẹpẹtẹ ti wọn ji kó lọ si Òkè-Òkun.

Díẹ̀ ninú àwọn Òṣèlú ti Ilé Iṣẹ́ Agbógun ti Ìwà Ìbàjẹ́ fi ẹ̀sùn kàn: Some of the Politicians facing corrupt charges by Economic and Financial Crimes Commission (EFCC)

Ẹ̀bẹ̀ la bẹ̀ “Òṣèlú Nigeria” ki wọn ma pe Ajá l’Ọbọ fún ará ilú, ki wọn kó owó ilú ti wọn ji pamọ́ si Òkè-Òkun padà, ki wọn si fi àpẹrẹ rere silẹ̀ fún ará ilú nipa àyipadà kúrò ni iwà ojúkòkòrò àti olè ti wọn nfi ipò jà dúró.  Àyipadà Òṣèlú kúrò ninú iwà burúkú ni ó lè mú ki owó ilú (Naira) kògè.

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button

“Olóyè Hannah Ìdòwú Dideolú Awólọ́wọ̀, Iyalode Rẹ́mọ, Yèyé Oòduà relé pẹ̀lú ijó àti ayọ̀” – “Chief (Mrs) Hannah Idowu Dideolu Awolowo, Remo Women Leader, Mother of Oodua departed with pomp and pageantry”

A bi Olóògbé, Olóyè Hannah Ìdòwú Dideolú ni ọjọ́ karundinlọ́gbọ̀n, oṣù kọkanla, ọdún Ẹ̀dẹ́ẹ́gbãlemẹ̃dógún, ó ṣe igbéyàwó pẹ̀lú Olóògbé Olóyè Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ̀ àgbà Òṣèlú ni ọjọ́ kẹrindinlọ́gbọ̀n, oṣù kejila, Ẹ̀dẹ́ẹ́gbãlemẹ̃tadinlọ́gbọ̀n, o jade láyé nigbati ó kú bi oṣú meji ó lé di ẹ ki ó pé ọgọrun ọdún.Image result for h i d awolowo burial

“Lẹhin ọkùnrin tàbi obinrin (ni ayé òde òni) ti ó bá ṣe ori-ire, obinrin tàbi ọkunrin rere wa lẹhin tabi ẹ̀gbẹ rẹ”.  Òwe yi ni a lè fi ṣe àpẹrẹ iṣẹ́ ribiribi ti Olóògbé, Olóyè Hannah Ìdòwú Dideolú ṣe fún Olóògbé Olóyè Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ̀, ògúná gbongbo Òṣèlú ni ilẹ̀ Yorùbá àti fún orilẹ̀ èdè Nigeria.  Nigbati Bàbá mba iṣẹ́ oselu kiri gbogbo àgbáyé, Iyá ló di ilé mú, ti ọkàn Olóògbé Olóyè Ọbáfẹ́mi Awólọ́wọ̀ fi balẹ̀ lati le fi ipò Olóri Òsèlú ṣe iṣẹ́ ribiribi ti ó ṣe.  Titi di ọjọ́ ikú ọkọ rẹ ni ọdún mejidinlọ́gbọ̀n sẹhin, lẹhin igbéyàwó àádọ́ta ọdún, ó ṣe àti lẹhin fún ọkọ rẹ titi di ọjọ́ alẹ́, eyi jẹ àpẹrẹ rere fún gbogbo obinrin.

Ẹbi àti ará ti bẹ̀rẹ̀ si palẹ̀mọ́ fún ọjọ́ ibi ọgọrun fún Olóògbé, Olóyè Hannah Ìdòwú Dideolú nigbati iròyin ikú rẹ jade pé iyá sùn ni ọjọ kọkàndinlógún, oṣú kẹsan ọdún Ẹgbàálemẹ̃dógún.  Ipalẹ̀mọ́ ìsìnku bẹ̀rẹ lati ṣe àṣeyẹ ikẹhin fún olóògbé dipò ayẹyẹ ọjọ́ ọgọrun ibi. 

Olóri Òṣèlú Nigeria Muhammadu Buhari pẹ̀lú àwọn àgbà Òsèlú, àwọn Ọba àti  Ìjòyè, ọmọdé àti àgbà ilú dara pọ̀ pẹ̀lú ẹbi àti àwọn ọmọ Olóògbé lati ṣe ẹ̀yẹ ikẹhin fún Olóògbé, Olóyè Hannah Ìdòwú Dideolú Awólọ́wọ̀ ni ọjọ́ karùndinlọ́gbọ̀n, oṣù kọkanla ọdún Ẹgbàálemẹ̃dógún.

Sùn re o, ó digbà, o di gbóṣe.

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button

Ọọ̀ni Ilé Ifẹ̀, Ọba Okùnadé Alade Sijúwadé, Olúbùṣe Keji Wàjà – The Ooni of Ife, King Okunade Alade Sijuwade has joined his Ancestors

Olóògbé Ọba Sijúwadé Olúbùṣe Keji - Late King Sijuwade, Olubuse II.

Olóògbé Ọba Sijúwadé Olúbùṣe Keji – Late King Sijuwade, Olubuse II.

Ni ọjọ Kejidinlọ́gbọ̀n, oṣù Keje, ọdún Ẹgbãlemẹ͂dógún, iroyin jade ninú àwọn iwé-iroyin àti ori ayélujára pé Ọba Okunade Sijuwade, Olúbùṣe Keji, pa ipò da ni Ilú Ọba.  Àwọn Olóyè Ilé-Ifẹ̀ sẹ́ ọ̀rọ̀ ikú Ọba yi, nitori ni ayé àtijọ́, àwọn àgbà Oyè ló ni àṣẹ lati tú ọ̀fọ̀ pé Ọba wàjà fún ará ilú, nitori gẹ́gẹ́ bi àṣà Yorùbá Ọba ki kú.  Àwọn àgbà Oyè tú ọ̀fọ̀ ni iwá́jú Gómìnà Rauf Arégbẹ́ṣọlá ti ipinlẹ̀ Ọ̀ṣun, ni Ọjọ́rú, ọjọ́ kejila oṣù kẹjọ ọdún Ẹgbãlemẹ͂dógún. Ni ayé òde òni kò si àṣiri mọ, àṣà yi ti yi padà nitori, ni àtijọ́, Ọba ki kú si àjò, bẹni kò si iwé-iroyin àti ẹ̀rọ ayélujára.

Ilé Ifẹ̀ jẹ́ ilú pàtàki ni ilẹ̀ Yorùbá nitori itàn sọ wi pé ibẹ̀ ni orisun Yorùbá pẹ̀lú Bàbá nla Yorùbá “Oduduwa” ti ó tẹ ibẹ̀ dó.   Okùnadé Alade Sijúwadé, Olúbùṣe Keji, gun ori oyè Ọọni Ifẹ̀ nigbati ó pé aadọta ọdún, ó lo ọdún mẹ͂dógóji ni ipò Ọọni Ifẹ̀.  Ohun ni aadọta Ọba Ilé Ifẹ̀.

Ìsìnkú Ọba Sijúwadé bẹ̀rẹ̀ ni ọjọ́ Ẹti, ọjọ́ kẹrinla, oṣù Kẹjọ, ọdún Ẹgbãlemẹ̃dógún.  Lẹhin ìsìnkú, ìséde ọlọ́jọ́ meje yio bẹ̀rẹ̀ ni Ilé-Ifẹ̀ àti agbègbè rẹ lati agogo mẹrin ìrọ̀lẹ́. Ki Èdùmàrè gba olóògbé Ọba Sijúwadé si afẹ́fẹ́ rere.

ENGLISH TRANSLATION Continue reading

Share Button